1 Mo fẹ́ ọ, Olúwa, agbára mi.
2 Olúwa ni àpáta àti odi mi, àti olùgbàlà mi;
3 Mo ké pe Olúwa, ẹni tí ìyìn yẹ fún,
4 Ìrora ikú yí mi kà,
5 Okùn isà òkú yí mi ká,
6 Nínú ìpọ́njú mo ké pe Olúwa;
7 Ayé wárìrì, ó sì mì tìtì,
8 Èéfín ti ihò imú rẹ̀ jáde wá;
9 Ó pín àwọn ọ̀run, Ó sì jáde wá;
10 Ó gun orí kérúbù, ó sì fò;
11 Ó fi òkùnkùn ṣe ibojì rẹ̀, ó fi ṣe ìbòrí yí ara rẹ̀ ká
12 Nípa ìmọ́lẹ̀ iwájú rẹ̀, àwọsánmọ̀ ṣíṣú dudu rẹ kọjá lọ
13 Olúwa sán àrá láti ọ̀run wá;
14 Ó ta àwọn ọfà rẹ̀, ó sì tú àwọn ọ̀tá náà ká,
15 A sì fi ìsàlẹ̀ àwọn òkun hàn,
16 Ó sọ̀kalẹ̀ láti ibi gíga, ó sì dì mímú;
17 Ó gbà mí kúrò lọ́wọ́ ọ̀tá mi alágbára,
18 Wọ́n dojúkọ mí ní ọjọ́ ìpọ́njú mi;
19 Ó mú mi jáde wá sínú ibi ńlá;
20 Olúwa ti hùwà sí mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi;
21 Nítorí mo ti pa ọ̀nà Olúwa mọ́;
22 Gbogbo òfin rẹ̀ ni ó wà níwájú mi;
23 Mo ti jẹ́ aláìlẹ́bi níwájú rẹ̀;
24 Olúwa san ẹ̀san fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi;
25 Fún olóòtítọ́ ni ìwọ ó fi ara rẹ̀ hàn ní olóòtítọ́,
26 sí ọlọ́kàn mímọ́, ìwọ ó fi ara rẹ̀ hàn ní ọlọ́kàn mímọ́,
27 O pa onírẹ̀lẹ̀ mọ́,
28 Ìwọ, Olúwa, jẹ́ kí fìtílà mi
29 Pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ rẹ̀, èmi sáré tọ ogun lọ;
30 Bí ó ṣe ti Ọlọ́run mi, ọ̀nà rẹ̀ pé,
31 Nítorí ta ni ṣe Ọlọ́run bí kò ṣe Olúwa?
32 Ọlọ́run ni ẹni tí ó fi agbára dì mí ní àmùrè
33 Ó ṣe ẹsẹ̀ mi gẹ́gẹ́ bi ẹsẹ̀ abo àgbọ̀nrín;
34 Ó kọ́ ọwọ́ mi ni ogun jíjà;
35 Ìwọ fi asà ìṣẹ́gun rẹ̀ fún mi,
36 Ìwọ sọ ìrìn ẹsẹ̀ mi di ńlá ní ìsàlẹ̀ mi,
37 Èmi lépa àwọn ọ̀tá mi, èmi sì bá wọn
38 Èmi sá wọn ní ọgbẹ́ tí wọn ko fi le è dìde;
39 Nítorí ìwọ fi agbára dì mí ní àmùrè fún ogun náà;
40 Ìwọ yí ẹ̀yìn àwọn ọ̀tá mí padà sí mi
41 Wọ́n kígbe fún ìrànlọ́wọ́, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan tí ó gbà wọ́n,
42 Mo lù wọ́n gẹ́gẹ́ bí eruku níwájú afẹ́fẹ́;
43 Ìwọ ti gbà mí lọ́wọ́ ìkọlù àwọn ènìyàn;
44 ni wéré ti wọ́n gbọ́ ohùn mi, wọ́n pa àṣẹ mi mọ́;
45 Àyà yóò pá àlejò;
46 Olúwa wà láààyè! Olùbùkún ni àpáta mi!
47 Òun ni Ọlọ́run tí ó ń gbẹ̀san mi,
48 tí ó pa mí mọ́ kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mí.
49 Títí láéláé, èmi yóò máa yìn ọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ìwọ Olúwa;
50 Ó fún ọba rẹ̀ ni ìṣẹ́gun ńlá;