1 Gbọ́, Olúwa, ẹ̀bẹ̀ òtítọ́ mi;
2 Kí ìdáláre mi wá láti ọ̀dọ̀ rẹ;
3 Ìwọ ti dán àyà mi wò,
4 Bí ó ṣe ti iṣẹ́ ènìyàn nípa ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ,
5 Ìrìn mí ti jẹ mọ́ ọ̀nà rẹ;
6 Èmi ké pè ọ́, Ọlọ́run, nítorí tí ìwọ yóò dá mi lóhùn
7 Fi ìṣeun ìyanu ìfẹ́ ńlá rẹ hàn
8 Pa mí mọ́ bí ẹyin ojú rẹ;
9 lọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú tí ń fóròó mi,
10 Wọ́n pa ọkàn aláìláàánú wọn mọ́,
11 Wọ́n sì mú mi mọ́lẹ̀, wọ́n sì yí mi ká,
12 Wọn dàbí i kìnnìún tí ebi ń pa fún ìjẹ,
13 Dìde, Olúwa, dojúkọ wọ́n, rẹ̀ wọ́n sílẹ̀;
14 Olúwa, nípa ọwọ́ rẹ, gbà mí kúrò lọ́wọ́ irú àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀,
15 Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi yóò máa wo ojú rẹ ní òdodo;