1 Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi.
2 Ìwọ fi ìmọ́lẹ̀ bo ara rẹ gẹ́gẹ́ bí aṣọ;
3 ìwọ tí ó fi omi ṣe ìtì igi àjà ìyẹ̀wù rẹ.
4 Ó fi ẹ̀fúùfù ṣe àwọn ìránṣẹ́ rẹ,
5 O fi ayé gúnlẹ̀ lórí àwọn ìpìlẹ̀;
6 Ìwọ fi ibú omi bò ó mọ́lẹ̀ bí aṣọ;
7 Ṣùgbọ́n nípa ìbáwí rẹ ni àwọn omi lọ,
8 wọ́n sàn kọjá lórí àwọn òkè,
9 Ìwọ gbé òpin tí wọn kò lè kọjá rẹ̀ kálẹ̀;
10 Ìwọ mú kí ìsun da omi sí àwọn àfonífojì;
11 Wọ́n fún gbogbo àwọn ẹranko igbó ní omi
12 Àwọn ẹyẹ ojú òfúrufú tẹ́ ìtẹ́ wọn lẹ́gbẹ̀ẹ́ omi
13 Ó bu omi rin àwọn òkè láti ìyẹ̀wù rẹ̀ wá;
14 Ó mú kí koríko hù jáde fún àwọn ẹranko láti jẹ
15 Ọtí wáìnì tí ó ń mú ọkàn ènìyàn yọ̀,
16 Àwọn igi Olúwa ni a bu omi rin dáradára,
17 Níbẹ̀ ní àwọn ẹyẹ ṣe ìtẹ́ wọn
18 Àwọn òkè gíga ni ààbò fún àwọn ewúrẹ́ igbó;
19 Òṣùpá jẹ́ àmì fún àkókò
20 Ìwọ mú òkùnkùn wá, ó sì di òru,
21 Kìnnìún ń bú ramúramù fún ohun ọdẹ wọn
22 Oòrùn ràn, wọ́n sì kó ara wọn jọ,
23 Ọkùnrin jáde lọ sí iṣẹ́ wọn,
24 Iṣẹ́ rẹ ti pọ̀ tó, Olúwa!
25 Bẹ́ẹ̀ ni Òkun yìí tí ó tóbi, tí ó sì ni ìbú,
26 Níbẹ̀ ni ọkọ̀ ń lọ síwá sẹ́yìn,
27 Àwọn wọ̀nyí ń wò ọ́
28 Nígbà tí ìwọ bá fi fún wọn,
29 Nígbà tí ìwọ bá pa ojú rẹ mọ́
30 Nígbà tí ìwọ rán ẹ̀mí rẹ,
31 Jẹ́ kí ògo Olúwa wà pẹ́ títí láé;
32 ẹni tí ó wo ayé, tí ó sì wárìrì,
33 Ní gbogbo ayé mi ní n ó kọrin sí Olúwa:
34 Jẹ́ kí ẹ̀kọ́ mi kí ó tẹ́ ọ lọ́rùn
35 Ṣùgbọ́n kí ẹlẹ́ṣẹ̀ kúrò láyé