1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀,
2 Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i;
3 Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀,
4 Wá Olúwa àti ipá rẹ̀;
5 Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe,
6 ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀,
7 Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa:
8 Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé,
9 májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu,
10 Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ,
11 “Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani
12 Nígbà tí wọn kéré níye,
13 wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè,
14 Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú;
15 “Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
16 Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà
17 Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn
18 Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀
19 títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ
20 Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀
21 Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀,
22 gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa
23 Israẹli wá sí Ejibiti;
24 Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i
25 Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn
26 Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀,
27 Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn
28 Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú
29 Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀,
30 Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá,
31 Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde,
32 Ó sọ òjò di yìnyín,
33 Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn
34 Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé,
35 wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn,
36 Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn,
37 Ó mú Israẹli jáde
38 Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ,
39 Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí,
40 Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá,
41 Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde;
42 Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀
43 Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde
44 Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà,
45 kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́