1 Ǹjẹ́ ọgbọ́n kò ha ń kígbe síta?
2 Ní ibi gíga ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà,
3 ní ẹgbẹ́ ibodè tí ó wọ ìlú,
4 “Sí i yín ẹ̀yin ènìyàn, ní mo ń kígbe pè;
5 Ẹ̀yin aláìmọ̀kan, ẹ kọ́gbọ́n;
6 Ẹ gbọ́, nítorí tí èmi ó sọ̀rọ̀ ohun iyebíye;
7 ẹnu mi ń sọ ohun tí í ṣe òtítọ́,
8 Gbogbo ọ̀rọ̀ ẹnu mi ni ó tọ́,
9 Fún olóye gbogbo rẹ̀ ni ó tọ̀nà;
10 Yan ẹ̀kọ́ mi dípò fàdákà,
11 nítorí ọgbọ́n ṣe iyebíye jù iyùn lọ,
12 “Èmi, ọgbọ́n ń gbé pẹ̀lú òye;
13 Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìkórìíra ibi
14 Ìmọ̀ràn àti ọgbọ́n tí ó yè kooro jẹ́ tèmi
15 Nípasẹ̀ mi ni ọba ń ṣàkóso
16 Nípasẹ̀ mi àwọn ọmọ-aládé ń ṣàkóso,
17 Mo fẹ́ràn àwọn tí ó fẹ́ràn mi,
18 Lọ́dọ̀ mi ni ọrọ̀ àti ọlá wà,
19 Èso mi dára ju wúrà dáradára lọ;
20 Mò ń rìn ní ọ̀nà òdodo,
21 mò ń fi ọrọ̀ fún gbogbo àwọn tí ó fẹ́ràn mi
22 “Èmi ni Olúwa kọ́kọ́ dá nínú iṣẹ́ rẹ̀.
23 a ti yàn mí láti ayérayé,
24 Nígbà tí kò tí ì sí Òkun, ni a ti bí mi,
25 kí a tó fi àwọn òkè sí ipò wọn,
26 kí ó tó dá ilẹ̀ ayé tàbí àwọn oko rẹ̀
27 Mo wà níbẹ̀ nígbà tí ó fi àwọn ọ̀run sí ipò wọn,
28 nígbà tí ó ṣẹ̀dá òfúrufú lókè
29 nígbà tí ó ṣe ààlà fún omi Òkun
30 Nígbà náà èmi ni gbẹ́nàgbẹ́nà ẹ̀gbẹ́ rẹ̀
31 Mo ń yọ̀ nínú gbogbo àgbáyé tí ó dá
32 “Nítorí náà báyìí, ẹ̀yin ọmọ mi,
33 Fetí sí ìtọ́sọ́nà mi kí o sì gbọ́n;
34 Ìbùkún ni fún ẹni tí ó fetísílẹ̀ sí mi,
35 Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá rí mi rí ìyè
36 Ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti rí ń pa ara rẹ̀ lára