Provérbios 8

YOR

1 Ǹjẹ́ ọgbọ́n kò ha ń kígbe síta?

2 Ní ibi gíga ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà,

3 ní ẹgbẹ́ ibodè tí ó wọ ìlú,

4 “Sí i yín ẹ̀yin ènìyàn, ní mo ń kígbe pè;

5 Ẹ̀yin aláìmọ̀kan, ẹ kọ́gbọ́n;

6 Ẹ gbọ́, nítorí tí èmi ó sọ̀rọ̀ ohun iyebíye;

7 ẹnu mi ń sọ ohun tí í ṣe òtítọ́,

8 Gbogbo ọ̀rọ̀ ẹnu mi ni ó tọ́,

9 Fún olóye gbogbo rẹ̀ ni ó tọ̀nà;

10 Yan ẹ̀kọ́ mi dípò fàdákà,

11 nítorí ọgbọ́n ṣe iyebíye jù iyùn lọ,

12 “Èmi, ọgbọ́n ń gbé pẹ̀lú òye;

13 Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìkórìíra ibi

14 Ìmọ̀ràn àti ọgbọ́n tí ó yè kooro jẹ́ tèmi

15 Nípasẹ̀ mi ni ọba ń ṣàkóso

16 Nípasẹ̀ mi àwọn ọmọ-aládé ń ṣàkóso,

17 Mo fẹ́ràn àwọn tí ó fẹ́ràn mi,

18 Lọ́dọ̀ mi ni ọrọ̀ àti ọlá wà,

19 Èso mi dára ju wúrà dáradára lọ;

20 Mò ń rìn ní ọ̀nà òdodo,

21 mò ń fi ọrọ̀ fún gbogbo àwọn tí ó fẹ́ràn mi

22 “Èmi ni Olúwa kọ́kọ́ dá nínú iṣẹ́ rẹ̀.

23 a ti yàn mí láti ayérayé,

24 Nígbà tí kò tí ì sí Òkun, ni a ti bí mi,

25 kí a tó fi àwọn òkè sí ipò wọn,

26 kí ó tó dá ilẹ̀ ayé tàbí àwọn oko rẹ̀

27 Mo wà níbẹ̀ nígbà tí ó fi àwọn ọ̀run sí ipò wọn,

28 nígbà tí ó ṣẹ̀dá òfúrufú lókè

29 nígbà tí ó ṣe ààlà fún omi Òkun

30 Nígbà náà èmi ni gbẹ́nàgbẹ́nà ẹ̀gbẹ́ rẹ̀

31 Mo ń yọ̀ nínú gbogbo àgbáyé tí ó dá

32 “Nítorí náà báyìí, ẹ̀yin ọmọ mi,

33 Fetí sí ìtọ́sọ́nà mi kí o sì gbọ́n;

34 Ìbùkún ni fún ẹni tí ó fetísílẹ̀ sí mi,

35 Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá rí mi rí ìyè

36 Ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti rí ń pa ara rẹ̀ lára

Ler em outra tradução

Comparar lado a lado