1 Mó kígbe sí Ọlọ́run fún ìrànlọ́wọ́;
2 Nígbà tí mo wà nínú ìpọ́njú,
3 Èmi rántí rẹ, Ọlọ́run,
4 Ìwọ kò fẹ́ kí èmi fi ojú ba oorun,
5 Mo ronú nípa ọjọ́ ìgbàanì;
6 mo rántí orin mi ní òru.
7 “Olúwa yóò ha kọ̀ títí láé?
8 Ṣe ìfẹ́ rẹ̀ àti àánú rẹ̀ ti kú lọ láéláé?
9 Ọlọ́run ha gbàgbé láti máa ṣàánú?
10 Èmi wí pé, “Èyí ní ẹ̀dùn ọkàn mi,
11 Èmi ó rántí iṣẹ́ Olúwa:
12 Èmi ṣàṣàrò lórí iṣẹ́ rẹ gbogbo,
13 Ọlọ́run, ọ̀nà rẹ jẹ́ mímọ́.
14 Ìwọ ni Ọlọ́run tó ń ṣe ìyanu;
15 Pẹ̀lú ọwọ́ agbára rẹ ni ìwọ ra àwọn ènìyàn padà,
16 Nígbà tí àwọn omi rí Ọlọ́run,
17 Àwọn ojú ọ̀run tú omi sílẹ̀,
18 Àrá rẹ̀ ni a gbọ́ nínú ìjì,
19 Ipa rẹ̀ gba Òkun, ọ̀nà rẹ̀ ń bẹ nínú Òkun,
20 Ó tọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran