1 Nítòótọ́ Ọlọ́run dára fún Israẹli,
2 Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi, ẹsẹ̀ mi ti yẹ̀ tán;
3 Nítorí èmi ń ṣe ìlara àwọn tó ń ṣe féfé
4 Wọn kò ṣe wàhálà;
5 Wọn kò ní ìpín nínú àjàgà tó ń ṣẹlẹ̀ sí ènìyàn;
6 Ìgbéraga ni ọ̀ṣọ́ ọrùn wọn;
7 Láti inú ọkàn àrékérekè ni àìṣòdodo ti wá;
8 Wọn ń ṣẹ̀sín, wọn sì ń sọ̀rọ̀-òdì ní ti ìnilára,
9 Wọ́n ń gbé ẹ̀mí wọn lé ọ̀run
10 Nítorí náà àwọn ènìyàn wọn yípadà sí wọn
11 Wọ́n wí pé, “Báwo ni Ọlọ́run yóò ṣe mọ̀?
12 Bí àwọn ènìyàn búburú ṣe rí nìyí,
13 Nítòótọ́ nínú asán ni mo pa ọkàn mi mọ́;
14 Ní gbogbo ọjọ́ ni a ń yọ mí lẹ́nu;
15 Bí mo bá wí pé, “Èmi ó wí báyìí,”
16 Nígbà tí mo gbìyànjú láti mọ èyí,
17 títí mo fi wọ ibi mímọ́ Ọlọ́run;
18 Lóòtítọ́ ìwọ gbé wọn lórí ilẹ̀ yíyọ́
19 Báwo ní a ti mú wọn lọ sínú ìdahoro yìí
20 Bí àlá nígbà tí ènìyàn bá jí,
21 Nígbà tí inú mi bàjẹ́
22 mo jẹ́ aṣiwèrè àti aláìlóye;
23 Síbẹ̀ mo wà pẹ̀lú rẹ nígbà gbogbo;
24 Ìwọ fi ìmọ̀ràn rẹ tọ́ mi
25 Ta ni mo ní ní ọ̀run, bí kò ṣe ìwọ?
26 Ara mi àti ọkàn mi le è kùnà
27 Àwọn tí ó jìnnà sí ọ yóò ṣègbé
28 Ṣùgbọ́n ní ti èmi, ó dára láti súnmọ́ Ọlọ́run.