Salmos 38

YOR

1 Olúwa, má ṣe bá mi wí nínú ìbínú rẹ,

2 Nítorí tí ọfà rẹ kàn mọ́ mi ṣinṣin,

3 Kò sí ibi yíyè ní ara à mi, nítorí ìbínú rẹ;

4 Nítorí àìṣedéédéé mi ti borí mi mọ́lẹ̀;

5 Ọgbẹ́ mi ń rùn ó sì díbàjẹ́

6 Èmi ń jòwèrè, orí mi tẹ̀ ba gidigidi

7 Nítorí ẹ̀gbẹ́ mi kún fún ìgbóná tí ń jóni

8 Ara mi hù, a sì wó mi jẹ́gẹjẹ̀gẹ;

9 Olúwa, gbogbo ìfẹ́ mi ń bẹ níwájú rẹ;

10 Àyà mi ń mí hẹlẹ, agbára mi yẹ̀ mí sílẹ̀;

11 Àwọn ọ̀rẹ́ mi àti àwọn ẹlẹgbẹ́ mi dúró lókèèrè réré kúrò níbi ìpọ́njú mi,

12 Àwọn tí n wá ẹ̀mí mi dẹ okùn sílẹ̀ fún mi;

13 Ṣùgbọ́n mo dàbí adití odi, èmi kò gbọ́ ọ̀rọ̀;

14 Nítòótọ́, mo rí bí ọkùnrin tí kò gbọ́rọ̀,

15 Ṣùgbọ́n sí ọ Olúwa, ìwọ ni mo dúró dè;

16 Nítorí tí mo gbàdúrà, “Gbóhùn mi, kí wọn má ba à yọ̀ mí;

17 Nítorí tí mo ti ṣetán láti ṣubú,

18 Mo jẹ́wọ́ ìrékọjá mi;

19 Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí pàtàkì, wọ́n lágbára púpọ̀,

20 Àwọn tí wọn ń fi ibi san rere fún mi

21 Má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀, ìwọ Olúwa!

22 Yára láti ràn mí lọ́wọ́,

Ler em outra tradução

Comparar lado a lado