1 Olúwa, má ṣe bá mi wí nínú ìbínú rẹ,
2 Nítorí tí ọfà rẹ kàn mọ́ mi ṣinṣin,
3 Kò sí ibi yíyè ní ara à mi, nítorí ìbínú rẹ;
4 Nítorí àìṣedéédéé mi ti borí mi mọ́lẹ̀;
5 Ọgbẹ́ mi ń rùn ó sì díbàjẹ́
6 Èmi ń jòwèrè, orí mi tẹ̀ ba gidigidi
7 Nítorí ẹ̀gbẹ́ mi kún fún ìgbóná tí ń jóni
8 Ara mi hù, a sì wó mi jẹ́gẹjẹ̀gẹ;
9 Olúwa, gbogbo ìfẹ́ mi ń bẹ níwájú rẹ;
10 Àyà mi ń mí hẹlẹ, agbára mi yẹ̀ mí sílẹ̀;
11 Àwọn ọ̀rẹ́ mi àti àwọn ẹlẹgbẹ́ mi dúró lókèèrè réré kúrò níbi ìpọ́njú mi,
12 Àwọn tí n wá ẹ̀mí mi dẹ okùn sílẹ̀ fún mi;
13 Ṣùgbọ́n mo dàbí adití odi, èmi kò gbọ́ ọ̀rọ̀;
14 Nítòótọ́, mo rí bí ọkùnrin tí kò gbọ́rọ̀,
15 Ṣùgbọ́n sí ọ Olúwa, ìwọ ni mo dúró dè;
16 Nítorí tí mo gbàdúrà, “Gbóhùn mi, kí wọn má ba à yọ̀ mí;
17 Nítorí tí mo ti ṣetán láti ṣubú,
18 Mo jẹ́wọ́ ìrékọjá mi;
19 Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí pàtàkì, wọ́n lágbára púpọ̀,
20 Àwọn tí wọn ń fi ibi san rere fún mi
21 Má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀, ìwọ Olúwa!
22 Yára láti ràn mí lọ́wọ́,