1 Olúwa, gbógun ti àwọn tí ń gbóguntì mí;
2 Di asà àti àpáta mú,
3 Fa idà àti ọ̀kọ̀ yọ
4 Kí wọn kí ó dààmú,
5 Jẹ́ kí wọn dàbí ìyàngbò níwájú afẹ́fẹ́,
6 Jẹ́ kí ọ̀nà wọn kí ó ṣókùnkùn, kí ó sì máa yọ́,
7 Nítorí pé, ní àìnídìí ni wọ́n dẹ àwọ̀n wọn sílẹ̀ fún mi,
8 Kí ìparun kí ó wá sí orí rẹ̀ ní òjijì.
9 Nígbà náà ni ọkàn mi yóò yọ̀ nínú Olúwa,
10 Gbogbo egungun mi yóò wí pé,
11 Àwọn ẹlẹ́rìí èké dìde;
12 Wọ́n fi búburú san ìre fún mi;
13 Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni, nígbà tí wọn ń ṣe àìsàn, mo wọ aṣọ ọ̀fọ̀;
14 èmí ń lọ kiri bí ẹni ń ṣọ̀fọ̀
15 Ṣùgbọ́n nínú ìkọ̀sẹ̀ mi wọ́n sì yọ̀, wọ́n sì kó ara wọn jọ;
16 Bí àwọn àgàbàgebè tí ń ṣe ẹlẹ́yà ní àpèjẹ
17 Yóò ti pẹ́ tó Olúwa, tí ìwọ yóò máa wò wọ́n lọ?
18 Nígbà náà ni èmi yóò ṣọpẹ́ fún Ọ nínú àjọ ńlá;
19 Má ṣe jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi
20 Nítorí pé wọn kò sọ ọ̀rọ̀ àlàáfíà,
21 Wọ́n ya ẹnu wọn gbòòrò sí mi; wọ́n wí pé, “Háà! Háà!
22 Ìwọ́ ti rí i Olúwa; má ṣe dákẹ́!
23 Dìde! ru ara rẹ̀ sókè fún ààbò mi,
24 Ṣe ìdájọ́ mi, Olúwa Ọlọ́run mi, gẹ́gẹ́ bí òdodo rẹ,
25 Má ṣe jẹ́ kí wọn wí nínú ara wọn pé, “Háà! A ti rí ohun tí ọkàn wa ń fẹ́!”
26 Kí ojú kí ó tì wọ́n,
27 Jẹ́ kí àwọn tí ó fẹ́ ìdáláre mi
28 Nígbà náà ni ahọ́n mi yóò máa sọ̀rọ̀ òdodo rẹ,