1 Èmi yóò máa fi ìbùkún fún Olúwa nígbà gbogbo;
2 Ọkàn mí yóò máa ṣògo nínú Olúwa;
3 Gbé Olúwa ga pẹ̀lú mi;
4 Èmi wá Olúwa, ó sì dá mi lóhùn;
5 Wọ́n wò ó, ìmọ́lẹ̀ sì mọ́ wọn;
6 Ọkùnrin olùpọ́njú yí kígbe, Olúwa sì gbóhùn rẹ̀;
7 Angẹli Olúwa yí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀ ká
8 Tọ́ ọ wò kí o sì rí i wí pé Olúwa dára;
9 Ẹ bẹ̀rù Olúwa, ẹ̀yin ènìyàn rẹ̀ mímọ́,
10 Àwọn ọmọ kìnnìún a máa ṣe aláìní ebi a sì máa pa wọ́n;
11 Wá, ẹ̀yin ọmọ mi, fi etí sí mi;
12 Ta ni nínú yín tí ń fẹ́ ìyè, tí ó sì ń fẹ́ ọjọ́ púpọ̀;
13 Pa ahọ́n rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ibi
14 Yà kúrò nínú ibi kí o sì ṣe rere;
15 Ojú Olúwa ń bẹ lára àwọn olódodo;
16 Ojú Olúwa korò sí àwọn tí ń ṣe búburú;
17 Nígbà tí olódodo bá ké fún ìrànlọ́wọ́,
18 Olúwa súnmọ́ etí ọ̀dọ̀ àwọn oníròbìnújẹ́ ọkàn;
19 Ìpọ́njú àwọn olódodo pọ̀,
20 Ó pa gbogbo egungun wọn mọ́;
21 Ibi ni ó mú ikú ìkà wá,
22 Olúwa ra ọkàn àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ padà;