1 Ẹ yọ̀ nínú Olúwa, ẹ̀yin olódodo;
2 Ẹ yin Olúwa pẹ̀lú dùùrù;
3 Ẹ kọ orin tuntun sí i;
4 Nítorí pé ọ̀rọ̀ Olúwa dúró ṣinṣin,
5 Ó fẹ́ òtítọ́ àti ìdájọ́;
6 Nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ Olúwa ni a ṣe dá àwọn ọ̀run,
7 Ó kó àwọn omi òkun jọ gẹ́gẹ́ bí èyí tí ó wà nínú ìgò;
8 Jẹ́ kí gbogbo ayé kí ó bẹ̀rù Olúwa:
9 Nítorí tí ó sọ̀rọ̀, ó sì ti rí bẹ́ẹ̀;
10 Olúwa ti mú ìmọ̀ràn àwọn orílẹ̀-èdè wá sí asán;
11 Ìgbìmọ̀ Olúwa dúró títí ayérayé,
12 Ìbùkún ni fún orílẹ̀-èdè náà, Ọlọ́run ẹni tí Olúwa jẹ́ tirẹ̀,
13 Olúwa wò láti ọ̀run wá;
14 Níbi tí ó ti jókòó lórí ìtẹ́
15 ẹni tí ó ṣe àyà wọn bákan náà,
16 A kò gba ọba kan là nípasẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọmọ-ogun;
17 Ohun asán ni ẹṣin fún ìṣẹ́gun;
18 Wò ó, ojú Olúwa wà lára àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀,
19 Láti gba ọkàn wọn kúrò lọ́wọ́ ikú
20 Ọkàn wa dúró de Olúwa;
21 Ọkàn wa yọ̀ nínú rẹ̀,
22 Kí àánú rẹ, Olúwa, kí ó wà lára wa,