1 Háà! Olúwa, ọba yóò yọ̀ nínú agbára rẹ,
2 Nítorí pé ìwọ ti fi ìfẹ́ ọkàn rẹ̀ fún un,
3 Ìwọ ti fi àwọn ìbùkún oore kò ó ni ọ̀nà
4 Ó béèrè fún ìyè, ìwọ sì fi fún un,
5 Ògo rẹ̀ pọ̀ nípasẹ̀ ìṣẹ́gun tí o fi fún un;
6 Dájúdájú, ìwọ ti fi ìbùkún ayérayé fún un:
7 Ọba ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú Olúwa;
8 Ọwọ́ rẹ yóò wá gbogbo àwọn ọ̀tá a rẹ rí;
9 Nígbà tí ìwọ bá yọ
10 Ìwọ yóò pa ìrandíran wọn run kúrò lórí ilẹ̀,
11 Bí o tilẹ̀ jẹ́ wí pé wọ́n ro èrò ibi sí ọ
12 Nítorí pé ìwọ yóò mú wọn yí ẹ̀yìn wọn padà
13 Gbígbéga ni ọ́ Olúwa, nínú agbára rẹ;