Salmos 136

YOR

1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí tí ó ṣeun;

2 Ẹ fi ọpẹ́ fún Ọlọ́run àwọn ọlọ́run:

3 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa àwọn olúwa,

4 Fún Òun nìkan tí ń ṣiṣẹ́ ìyanu ńlá;

5 Fún ẹni tí ó fi ọgbọ́n dá ọ̀run;

6 Fún ẹni tí ó tẹ́ ilẹ̀ lórí omi;

7 Fún ẹni tí ó dá àwọn ìmọ́lẹ̀ ńlá;

8 Òòrùn láti jẹ ọba ọ̀sán;

9 Òṣùpá àti ìràwọ̀ láti jẹ ọba òru;

10 Fún ẹni tí ó kọlu Ejibiti lára àwọn àkọ́bí wọn;

11 Ó sì mú Israẹli jáde kúrò láàrín wọn;

12 Pẹ̀lú ọwọ́ agbára àti apá nínà;

13 Fún ẹni tí ó pín Òkun pupa ní ìyà;

14 Ó sì mú Israẹli kọjá láàrín rẹ̀

15 Ṣùgbọ́n ó bi Farao àti ogun rẹ̀ ṣubú nínú Òkun pupa;

16 Fún ẹni tí ó sin àwọn ènìyàn rẹ̀ la aginjù já

17 Fún ẹni tí ó kọlu àwọn ọba ńlá;

18 Ó sì pa àwọn ọba olókìkí

19 Sihoni, ọba àwọn ará Amori

20 Àti Ogu, ọba Baṣani;

21 Ó sì fi ilẹ̀ wọn fún ni ní ìní,

22 Ìní fún Israẹli, ìránṣẹ́ rẹ̀,

23 Ẹni tí ó rántí wa ní ìwà ìrẹ̀lẹ̀ wa;

24 Ó sì dá wa ní ìdè lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa;

25 Ẹni tí ó fi oúnjẹ fún àwọn ẹ̀dá gbogbo

26 Ẹ fi ọpẹ́ fún Ọlọ́run ọ̀run;

Ler em outra tradução

Comparar lado a lado