1 Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, àní ẹ kó ra yín jọ pọ̀
2 kí a tó pa àṣẹ náà, kí ọjọ́ náà tó kọjá bí ìyàngbò ọkà,
3 Ẹ wá Olúwa, gbogbo ẹ̀yin onírẹ̀lẹ̀ ilẹ̀ náà,
4 Nítorí pé, a ó kọ Gasa sílẹ̀,
5 Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ń gbé etí Òkun,
6 Ilẹ̀ náà ní etí Òkun, ni ibùgbé àwọn ará Kereti,
7 Agbègbè náà yóò sì jẹ́ ti ìyókù àwọn ilé Juda,
8 “Èmi ti gbọ́ ẹ̀gàn Moabu,
9 Nítorí náà, bí Èmi tí wà,”
10 Èyí ni ohun tí wọn yóò gbà padà nítorí ìgbéraga wọn,
11 Olúwa yóò jẹ́ ìbẹ̀rù fún wọn;
12 “Ẹ̀yin Etiopia pẹ̀lú,
13 Òun yóò sì na ọwọ́ rẹ̀ sí apá àríwá,
14 Agbo ẹran yóò sì dùbúlẹ̀ ni àárín rẹ̀,
15 Èyí ni ìlú aláyọ̀ tí ó ń gbé láìléwu.