1 Tẹ́tí, ẹ̀yin ọmọ mi, sí ẹ̀kọ́ baba; fetísílẹ̀ kí o sì ní òye sí i.
2 Mo fún ọ ní ẹ̀kọ́ tí ó yè kooro,
3 Nígbà tí mo jẹ́ ọ̀dọ́mọkùnrin ní ilé baba à mí,
4 Ó kọ́ mi ó sì wí pé,
5 Gba ọgbọ́n, gba òye,
6 Má ṣe kọ ọgbọ́n sílẹ̀, yóò sì dáàbò bò ọ́,
7 Ọgbọ́n ni ó ga jù; nítorí náà gba ọgbọ́n.
8 Gbé e ga, yóò sì gbé ọ ga
9 Yóò fi òdòdó ọ̀ṣọ́ ẹwà sí orí rẹ
10 Tẹ́tí, ọmọ mi, gba ohun tí mo sọ,
11 Mo tọ́ ọ ṣọ́nà ní ọ̀nà ti ọgbọ́n
12 Nígbà tí o rìn, ìgbésẹ̀ rẹ kò ní ní ìdíwọ́
13 Di ẹ̀kọ́ mú, má ṣe jẹ́ kí ó lọ;
14 Má ṣe gbé ẹsẹ̀ rẹ sí ojú ọnà àwọn ènìyàn búburú
15 Yẹra fún un, má ṣe rìn níbẹ̀;
16 Nítorí wọn kò le sùn àyàfi tí wọ́n bá ṣe ibi,
17 Wọ́n ń jẹ oúnjẹ ìwà búburú
18 Ipa ọ̀nà olódodo dàbí àṣẹ̀ṣẹ̀yọ oòrùn
19 ṣùgbọ́n ọ̀nà ènìyàn búburú dàbí òkùnkùn biribiri;
20 Ọmọ mi, tẹ́tí sí ohun tí mo sọ;
21 Má ṣe jẹ́ kí wọ́n rá mọ́ ọ lójú
22 nítorí ìyè ni wọ́n jẹ́ fún gbogbo ẹni tí ó rí wọn
23 Ju gbogbo nǹkan tókù lọ, pa ọkàn rẹ mọ́,
24 Mú àrékérekè kúrò ní ẹnu rẹ;
25 Jẹ́ kí ojú rẹ máa wo iwájú,
26 Kíyèsi ìrìn ẹsẹ̀ rẹ
27 Má ṣe yà sọ́tùn ún tàbí sósì;