1 Ọmọ mi, bí ìwọ bá gba ọ̀rọ̀ mi,
2 tí ìwọ dẹtí rẹ sílẹ̀ sí ọgbọ́n
3 àní, bí ìwọ bá ké tọ ìmọ̀ lẹ́yìn,
4 bí ìwọ bá ṣàfẹ́rí rẹ̀ bí i fàdákà
5 Nígbà náà ni ìwọ yóò bẹ̀rù Olúwa,
6 Nítorí Olúwa ni ó ń fún ni ní ọgbọ́n,
7 Ó to ìgbàlà fún àwọn olódodo,
8 Ó pa ipa ọ̀nà ìdájọ́ mọ́
9 Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ òdodo àti ìdájọ́,
10 Nítorí ọgbọ́n yóò wọ inú ọkàn rẹ
11 Ìmòye yóò pa ọ mọ́
12 Ọgbọ́n yóò gbà ọ́ là kúrò ní ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú,
13 ẹni tí ó kúrò ní ọ̀nà ìdúró ṣinṣin
14 ẹni tí ó yọ̀ nínú ṣíṣe búburú,
15 ọ̀nà ẹni tí ó wọ́
16 Yóò gba ìwọ pẹ̀lú là kúrò lọ́wọ́ àwọn àjèjì obìnrin,
17 ẹni tí ó ti kọ ọkọ àkọ́fẹ́ ìgbà èwe rẹ̀ sílẹ̀
18 Nítorí ilé rẹ̀ jẹ́ ọ̀nà sí ikú
19 Kò sẹ́ni tó lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ tí ó padà
20 Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ yóò rìn ní ọ̀nà àwọn ènìyàn rere
21 Nítorí ẹni dídúró ṣinṣin yóò gbé ní ilé náà
22 Ṣùgbọ́n a ó ké ènìyàn búburú kúrò lórí ilẹ̀ náà