1 Àwọn òwe ti Solomoni, ọmọ Dafidi, ọba Israẹli.
2 Láti le ní ọgbọ́n àti ẹ̀kọ́,
3 Láti gba ẹ̀kọ́ ọgbọ́n, òdodo,
4 láti fi òye fún onírẹ̀lẹ̀,
5 Jẹ́ kí ọlọ́gbọ́n tẹ́tí kí ó sì ní ìmọ̀ kún ìmọ̀,
6 Láti mọ ìtumọ̀ òwe àti ìtán-dòwe,
7 Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìbẹ̀rẹ̀ ìmọ̀,
8 Tẹ́tí, ìwọ ọmọ mi sí ẹ̀kọ́ baba rẹ,
9 Wọn yóò jẹ́ òdòdó ẹ̀yẹ olóòórùn dídùn lórí rẹ
10 Ọmọ mi, bí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ bá ń tàn ọ́,
11 Bí wọn bá wí pé, “Wá pẹ̀lú wa;
12 jẹ́ ká gbé wọn mì láààyè, bí ibojì òkú,
13 a ó rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan tó níye lórí
14 da ìpín rẹ pọ̀ mọ́ àárín wa,
15 ọmọ mi, má ṣe bá wọn lọ,
16 Nítorí ẹsẹ̀ wọn ń sáré sí ẹ̀ṣẹ̀,
17 Wàhálà asán ni kí ènìyàn máa dẹ àwọ̀n sílẹ̀,
18 Àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ń lúgọ fún ẹ̀jẹ̀ ara wọn.
19 Báyìí ni ìgbẹ̀yìn gbogbo àwọn tí ń wá èrè àìtọ́;
20 Ọgbọ́n kígbe sókè ní pópó
21 láàrín ọjà ni ó ti kígbe jáde
22 “Yóò ha ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin aláìmọ̀kan yóò fi fẹ́ àìmọ̀kan yín tó?
23 Bí ẹ bá ti gbọ́ ìbáwí ì mi ni,
24 Ṣùgbọ́n níwọ̀n bí ẹ ti kọ ìpè ní ìgbà tí mo pè
25 níwọ́n bí ẹ ti kọ gbogbo ìmọ̀ràn mi,
26 Èmi pẹ̀lú yóò fi ìdààmú yín rẹ́rìn-ín;
27 Nígbà tí ìyọnu bá dé bá a yín bí ìjì líle,
28 “Nígbà náà ni wọn yóò ké pè mí ṣùgbọ́n, èmi kò ní dáhùn;
29 Níwọ́n bí wọ́n ti kórìíra ìmọ̀
30 Níwọ́n bí wọn kò ti gbà ìmọ̀ràn mi
31 wọn yóò jẹ èrè iṣẹ́ ọwọ́ wọn
32 Nítorí ìrìnkurìn àwọn aláìmọ̀kan ni yóò pa wọ́n
33 ṣùgbọ́n ẹnìkan tí ó bá fetí sí mi, yóò gbé láìléwu