1 Ìdáhùn pẹ̀lẹ́ yí ìbínú padà
2 Ahọ́n ọlọ́gbọ́n a máa gbé ìmọ̀ jáde
3 Ojú Olúwa wà níbi gbogbo,
4 Ahọ́n tí ń mú ìtura wá jẹ́ igi ìyè
5 Aláìgbọ́n ọmọ kọ ìbáwí baba rẹ̀
6 Ilé olódodo kún fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun ìṣúra,
7 Ètè olódodo ń tan ìmọ̀ kalẹ̀;
8 Olúwa kórìíra ìrúbọ àwọn ènìyàn búburú
9 Olúwa kórìíra ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú,
10 Ẹni tí ó kúrò lójú ọ̀nà yóò rí ìbáwí gan an,
11 Ikú àti ìparun ṣí sílẹ̀ níwájú Olúwa,
12 Ẹlẹ́gàn kò fẹ́ ẹni tí ń ba wí:
13 Inú dídùn máa ń mú kí ojú túká
14 Ọkàn olóye ń wá ìmọ̀
15 Gbogbo ọjọ́ àwọn olùpọ́njú jẹ́ ibi,
16 Ó sàn kí ó má pọ̀, kí ìbẹ̀rù Olúwa sì wà
17 Oúnjẹ ewébẹ̀ níbi tí ìfẹ́ wà
18 Ènìyàn onínú ríru dá ìjà sílẹ̀
19 Ọ̀nà ọ̀lẹ ni ẹ̀gún dí,
20 Ọlọ́gbọ́n ọmọ mú inú baba rẹ̀ dùn,
21 Inú ènìyàn aláìlóye a máa dùn sí ìwà òmùgọ̀;
22 Ìgbèrò a máa dasán níbi tí kò sí ìmọ̀ràn;
23 Inú ènìyàn a máa dùn nígbà tí ó bá fèsì tó yẹ
24 Ọ̀nà ìyè ń lọ sókè fún ọlọ́gbọ́n
25 Olúwa fa ilé onígbèéraga ya lulẹ̀,
26 Olúwa kórìíra èrò ènìyàn búburú, ṣùgbọ́n mímọ́ ni ọ̀rọ̀ ẹni pípé.
27 Ọ̀kánjúwà ènìyàn mú ìyọnu bá ilé rẹ̀
28 Ọkàn olódodo ń wọn ìdáhùn wò
29 Olúwa jìnnà sí ènìyàn búburú
30 Ojú tó túká máa ń mú ayọ̀ wá fún ọkàn,
31 Ẹni tí ó fetí sí ìbáwí tí ń fún ni ní ìyè,
32 Ẹni tí ó kọ̀ ìbáwí kẹ́gàn ara rẹ̀,
33 Ìbẹ̀rù Olúwa kọ́ ènìyàn ní ọgbọ́n,