1 Ọlọ́gbọ́n ọmọ gba ẹ̀kọ́ baba rẹ̀,
2 Láti inú èso ẹnu rẹ̀ ènìyàn ń gbádùn ohun rere,
3 Ẹnikẹ́ni tí ó ṣọ́ ẹnu rẹ̀ pa ẹnu ara rẹ̀ mọ́,
4 Ọkàn ọ̀lẹ ń fẹ́, ṣùgbọ́n kò rí nǹkan kan,
5 Olódodo kórìíra ohun tí í ṣe irọ́,
6 Òdodo ń ṣamọ̀nà ènìyàn olóòtítọ́ inú,
7 Ènìyàn kan díbọ́n bí ẹni tí ó ní ọrọ̀ síbẹ̀ kò ní nǹkan kan
8 Ọrọ̀ ènìyàn le è ra ẹ̀mí rẹ̀
9 Ìmọ́lẹ̀ olódodo tàn roro,
10 Ìgbéraga máa ń dá ìjà sílẹ̀ ni
11 Owó tí a fi ọ̀nà èrú kójọ yóò ṣí lọ,
12 Ìrètí tí ń falẹ̀ máa ń mú kí ọkàn ṣàárẹ̀
13 Ẹni tí ó kẹ́gàn ẹ̀kọ́ yóò jìyà rẹ̀
14 Ìkọ́ni ọlọ́gbọ́n jẹ́ orísun ìyè,
15 Òye pípé ń mú ni rí ojúrere,
16 Gbogbo olóye ènìyàn máa ń hùwà pẹ̀lú ìmọ̀,
17 Ìránṣẹ́ búburú bọ́ sínú ìdààmú
18 Ẹni tí ó kọ ìbáwí yóò di tálákà yóò sì rí ìtìjú,
19 Ìfẹ́ tí a mú ṣẹ dùn mọ́ ọkàn
20 Ẹni tí ó ń bá ọlọ́gbọ́n rìn yóò gbọ́n
21 Òsì a máa ta ẹlẹ́ṣẹ̀,
22 Ènìyàn rere a máa fi ogún sílẹ̀ fún àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀,
23 Ilẹ̀ ẹ tálákà le è mú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìre oko wá
24 Ẹni tí ó fa ọwọ́ ìbáwí sẹ́yìn kórìíra ọmọ rẹ̀
25 Olódodo jẹ́wọ́ títí ó fi tẹ́ ọkàn rẹ̀ lọ́rùn