1 Ẹnikẹ́ni tí ó fẹ́ ẹ̀kọ́ fẹ́ ìmọ̀,
2 Ènìyàn rere gba ojúrere lọ́dọ̀ Olúwa
3 A kò lè fi ẹsẹ̀ ènìyàn múlẹ̀ nípa ìwà búburú
4 Aya oníwà rere ni adé ọkọ rẹ̀
5 Èrò àwọn olódodo tọ́,
6 Ọ̀rọ̀ ènìyàn búburú lúgọ de ẹ̀jẹ̀
7 A ṣí àwọn ènìyàn búburú ní ìdí, wọn kò sì sí mọ́;
8 A ń yín ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀n ọgbọ́n rẹ̀
9 Ó sàn kí a má jẹ́ ènìyàn pàtàkì kí a sì ní ìránṣẹ́
10 Olódodo ènìyàn ń ṣe aájò ohun tí àwọn ohun ọ̀sìn rẹ̀ nílò,
11 Ẹni tí ó bá dá oko yóò ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ oúnjẹ,
12 Ènìyàn búburú ń fẹ́ ìkógun àwọn ènìyàn ìkà
13 A mú ènìyàn búburú nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀
14 Láti inú èso rẹ̀, ènìyàn kún fún onírúurú ohun rere
15 Ọ̀nà aláìgbọ́n dára lójú ara rẹ̀
16 Aláìgbọ́n ènìyàn fi ìbínú un rẹ̀ hàn lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀,
17 Ẹni tí ó jẹ́ ajẹ́rìí òtítọ́ jẹ́rìí ohun tí ojú rẹ̀ rí
18 Ọ̀rọ̀ tí a kò rò jinlẹ̀ máa ń gún ni bí ọ̀kọ̀
19 Ètè tí ń ṣọ òtítọ́ yóò wà láéláé
20 Ẹ̀tàn wà nínú ọkàn àwọn tí ń pète búburú
21 Ibi kì í ṣubú lu olódodo rárá
22 Olúwa kórìíra ètè tí ń parọ́
23 Ènìyàn olóye fi ìmọ̀ rẹ̀ pamọ́ sínú ara rẹ̀
24 Ọwọ́ àìṣọ̀lẹ yóò jẹ ọba
25 Ìbànújẹ́ ní ọkàn ènìyàn ní dorí rẹ̀ kodò
26 Olódodo ènìyàn máa ń ṣọ́ra láti dọ́rẹ̀ẹ́
27 Ọ̀lẹ ènìyàn kò sun ẹran tí ó pa lóko ọdẹ
28 Ní ọ̀nà àwọn olódodo ni ìyè wà