1 Àwọn òwe Solomoni.
2 Ìṣúra tí a kójọ nípa ìwà búburú kò ní èrè,
3 Olúwa kì í jẹ́ kí ebi máa pa olódodo,
4 Ọwọ́ tí ó lẹ máa ń sọ ènìyàn di tálákà,
5 Ẹni tí ó kó irúgbìn jọ ní àsìkò òjò jẹ́ ọlọ́gbọ́n ọmọ,
6 Ìbùkún ní ó máa ń kún orí olódodo,
7 Ìrántí olódodo yóò jẹ́ ìbùkún,
8 Ẹni tí ó gbọ́n nínú ọkàn rẹ̀ máa ń gba àṣẹ,
9 Ẹni tí ó ń rìn déédé, ń rìn láìléwu,
10 Ẹni tí ń ṣẹ́jú pàkòpàkò fún ibi ń fa àìbalẹ̀ ọkàn,
11 Ẹnu olódodo jẹ́ orísun ìyè,
12 Ìríra a máa dá ìjà sílẹ̀,
13 Ọgbọ́n ni a ń bá lẹ́nu àwọn olóye,
14 Ọlọ́gbọ́n ènìyàn kó ìmọ̀ jọ,
15 Ọrọ̀ àwọn olódodo ni ìlú olódi wọn,
16 Èrè olódodo ń mú ìyè wá fún wọn,
17 Ẹni tí ó gbọ́ ìbáwí fi ọ̀nà sí ìyè hàn,
18 Ẹni tí ó pa ìkórìíra rẹ̀ mọ́ jẹ́ òpùrọ́
19 Nínú ọ̀rọ̀ púpọ̀ a kò le fẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ kù
20 Ètè olódodo jẹ́ ààyò fàdákà,
21 Ètè olódodo ń bọ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀,
22 Ìbùkún Olúwa ń mú ọrọ̀ wá,
23 Aláìgbọ́n a máa ní inú dídùn sí ìwà búburú,
24 Ohun tí ènìyàn búburú bẹ̀rù yóò dé bá a;
25 Nígbà tí ìjì bá ti jà kọjá, ènìyàn búburú a kọjá lọ,
26 Bí ọtí kíkan sí eyín, àti èéfín sí ojú,
27 Ìbẹ̀rù Olúwa ń mú ọjọ́ ayé gígùn wá,
28 Ìrètí olódodo ni ayọ̀,
29 Ọ̀nà Olúwa jẹ́ ààbò fún olódodo,
30 A kì yóò fa olódodo tu láéláé,
31 Ẹnu olódodo ń mú ọgbọ́n jáde wá,
32 Ètè olódodo mọ ohun ìtẹ́wọ́gbà,