Provérbios 10

YOR

1 Àwọn òwe Solomoni.

2 Ìṣúra tí a kójọ nípa ìwà búburú kò ní èrè,

3 Olúwa kì í jẹ́ kí ebi máa pa olódodo,

4 Ọwọ́ tí ó lẹ máa ń sọ ènìyàn di tálákà,

5 Ẹni tí ó kó irúgbìn jọ ní àsìkò òjò jẹ́ ọlọ́gbọ́n ọmọ,

6 Ìbùkún ní ó máa ń kún orí olódodo,

7 Ìrántí olódodo yóò jẹ́ ìbùkún,

8 Ẹni tí ó gbọ́n nínú ọkàn rẹ̀ máa ń gba àṣẹ,

9 Ẹni tí ó ń rìn déédé, ń rìn láìléwu,

10 Ẹni tí ń ṣẹ́jú pàkòpàkò fún ibi ń fa àìbalẹ̀ ọkàn,

11 Ẹnu olódodo jẹ́ orísun ìyè,

12 Ìríra a máa dá ìjà sílẹ̀,

13 Ọgbọ́n ni a ń bá lẹ́nu àwọn olóye,

14 Ọlọ́gbọ́n ènìyàn kó ìmọ̀ jọ,

15 Ọrọ̀ àwọn olódodo ni ìlú olódi wọn,

16 Èrè olódodo ń mú ìyè wá fún wọn,

17 Ẹni tí ó gbọ́ ìbáwí fi ọ̀nà sí ìyè hàn,

18 Ẹni tí ó pa ìkórìíra rẹ̀ mọ́ jẹ́ òpùrọ́

19 Nínú ọ̀rọ̀ púpọ̀ a kò le fẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ kù

20 Ètè olódodo jẹ́ ààyò fàdákà,

21 Ètè olódodo ń bọ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀,

22 Ìbùkún Olúwa ń mú ọrọ̀ wá,

23 Aláìgbọ́n a máa ní inú dídùn sí ìwà búburú,

24 Ohun tí ènìyàn búburú bẹ̀rù yóò dé bá a;

25 Nígbà tí ìjì bá ti jà kọjá, ènìyàn búburú a kọjá lọ,

26 Bí ọtí kíkan sí eyín, àti èéfín sí ojú,

27 Ìbẹ̀rù Olúwa ń mú ọjọ́ ayé gígùn wá,

28 Ìrètí olódodo ni ayọ̀,

29 Ọ̀nà Olúwa jẹ́ ààbò fún olódodo,

30 A kì yóò fa olódodo tu láéláé,

31 Ẹnu olódodo ń mú ọgbọ́n jáde wá,

32 Ètè olódodo mọ ohun ìtẹ́wọ́gbà,

Ler em outra tradução

Comparar lado a lado