1 Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú
2 Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn
3 Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi
4 Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó
5 Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká
6 Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn,
7 Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ;
8 Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́,
9 Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi;
10 Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀,
11 Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀
12 Ó fa ọfà rẹ̀ yọ
13 Ó fa ọkàn mí ya
14 Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi;
15 Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò
16 Ó ti fi òkúta kán eyín mi;
17 Mo ti jìnnà sí àlàáfíà;
18 Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ
19 Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi,
20 Mo ṣèrántí wọn,
21 Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn
22 Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé,
23 Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀;
24 Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa;
25 Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀,
26 Ó dára kí a ní sùúrù
27 Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà
28 Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́,
29 Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku—
30 Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a,
31 Ènìyàn kò di ìtanù
32 Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn,
33 Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá
34 Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀
35 Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀
36 láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà,
37 Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀
38 Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ
39 Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn
40 Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò,
41 Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè
42 “Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀
43 “Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa;
44 Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ
45 Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn
46 “Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn
47 Àwa ti jìyà àti ìparun,
48 Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò
49 Ojú mi kò dá fún omijé,
50 títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀
51 Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi
52 Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí
53 Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò
54 Orí mi kún fún omi,
55 Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa,
56 Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ
57 O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́,
58 Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò,
59 O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi.
60 Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn,
61 Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn
62 ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ
63 Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde,
64 Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn
65 Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn,
66 Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú,