1 Jobu sì dáhùn ó sì wí pé,
2 “Èmi mọ̀ pe bẹ́ẹ̀ ni ní òtítọ́.
3 Bí ó bá ṣe pé yóò bá a jà,
4 Ọlọ́gbọ́n nínú àwọn alágbára ní ipa ní Òun.
5 Ẹni tí ó sí òkè nídìí tí wọn kò sì mọ́:
6 Tí ó mi ilẹ̀ ayé tìtì kúrò ní ipò rẹ̀,
7 Ó pàṣẹ fún oòrùn kò sì le è ràn,
8 Òun nìkan ṣoṣo ni ó ta ojú ọ̀run,
9 Ẹni tí ó dá ìràwọ̀ Beari àti Orioni,
10 Ẹni tí ń ṣe ohun tí ó tóbi jù àwárí lọ,
11 Kíyèsi i, ó ń kọjá lọ ní ẹ̀bá ọ̀dọ̀ mi, èmi kò sì rí i,
12 Kíyèsi i, ó já a gbà lọ, ta ni ó lè fà á padà?
13 Ọlọ́run kò ní fa ìbínú rẹ̀ sẹ́yìn,
14 “Kí ní ṣe tí èmi ti n o fi ba ṣàròyé?
15 Bí ó tilẹ̀ ṣe pé mo ṣe aláìlẹ́bi, èmi kò gbọdọ̀ dá a lóhùn;
16 Bí èmi bá sì ké pè é, tí Òun sì dá mi lóhùn,
17 Nítorí pé òun yóò lọ̀ mí lúúlúú pẹ̀lú ìjì ńlá,
18 Òun kì yóò jẹ́ kí èmi kí ó rí ẹ̀mí mi,
19 Bí mo bá sọ ti agbára, wò ó!
20 Bí mo tilẹ̀ dá ara mi láre, ẹnu ara mi yóò dá mi lẹ́bi;
21 “Olóòótọ́ ni mo ṣe,
22 Ohùn kan náà ni, nítorí náà ni èmi ṣe sọ:
23 Bí ìjàǹbá bá pa ni lójijì,
24 Nígbà tí a bá fi ayé lé ọwọ́ ènìyàn búburú;
25 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí ọjọ́ mi yára ju oníṣẹ́ lọ,
26 Wọ́n kọjá lọ bí ọkọ̀ eèsún papirusi tí ń sáré lọ;
27 Bí èmi bá wí pé, ‘Èmi ó gbàgbé arò ìbìnújẹ́ mi,
28 Ẹ̀rù ìbànújẹ́ mi gbogbo bà mí,
29 Bí ó bá ṣe pé ènìyàn búburú ni èmi,
30 Bí mo tilẹ̀ fi ọṣẹ dídì wẹ ara mi,
31 síbẹ̀ ìwọ ó gbé mi wọ inú ihò
32 “Nítorí Òun kì í ṣe ènìyàn bí èmi,
33 Bẹ́ẹ̀ ni kò sí alátúnṣe kan ní agbede-méjì wa
34 Kí ẹnìkan sá à mú ọ̀pá Ọlọ́run kúrò lára mi,
35 Nígbà náà ni èmi ìbá sọ̀rọ̀, èmi kì bá sì bẹ̀rù rẹ̀;