1 Ìgbà náà ni Bilidadi, ará Ṣuhi, sì dáhùn wí pé,
2 “Ìwọ yóò ti máa sọ nǹkan wọ̀nyí pẹ́ tó?
3 Ọlọ́run a ha máa yí ìdájọ́ po bí?
4 Nígbà tí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣẹ̀ sí i,
5 Bí ìwọ bá sì ké pe Ọlọ́run ní àkókò,
6 Ìwọ ìbá jẹ́ mímọ, kí ó sì dúró ṣinṣin:
7 Ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ ìbá tilẹ̀ kéré si í,
8 “Èmi bẹ̀ ọ́ ǹjẹ́, béèrè lọ́wọ́ àwọn ará ìgbà nì
9 Nítorí pé ọmọ-àná ni àwa, a kò sì mọ nǹkan,
10 Àwọn kì yóò wa kọ ọ́, wọn kì yóò sì sọ fún ọ?
11 Papirusi ha lè dàgbà láìní ẹrẹ̀
12 Nígbà tí ó wà ní tútù, tí a kò ké e lulẹ̀,
13 Bẹ́ẹ̀ ni ipa ọ̀nà gbogbo àwọn tí ó gbàgbé Ọlọ́run,
14 Àbá ẹni tí a ó kèé kúrò,
15 Yóò fi ara ti ilé rẹ̀, ṣùgbọ́n kì yóò lè dúró,
16 Ó tutù bí irúgbìn tí a bomirin níwájú oòrùn,
17 Gbòǹgbò rẹ̀ ta yí ebè ká,
18 Bí ó bá sì pa á run kúrò ní ipò rẹ̀,
19 Kíyèsi i, ayé rẹ̀ gbẹ dànù
20 “Kíyèsi i, Ọlọ́run kì yóò ta ẹni òtítọ́ nù,
21 títí yóò fi fi ẹ̀rín kún ọ ní ẹnu,
22 ìtìjú ní a o fi bo àwọn tí ó kórìíra rẹ̀,