1 “Ṣé ìjà kò ha si fún ènìyàn lórí ilẹ̀?
2 Bí ọmọ ọ̀dọ̀ tí máa ń kánjú bojú wo òjìji,
3 Bẹ́ẹ̀ ni a mú mi ní ìbànújẹ́ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ oṣù,
4 Nígbà ti mo dùbúlẹ̀, èmi wí pé, ‘Nígbà wo ni èmi ó dìde?’
5 Kòkòrò àti ògúlùtu erùpẹ̀ ni á fi wọ̀ mi ni aṣọ,
6 “Ọjọ́ mi yára jù ọkọ̀ ìhunṣọ lọ,
7 Háà! Rántí pé afẹ́fẹ́ ni ẹ̀mí mi;
8 Ojú ẹni tí ó rí mi, kì yóò rí mi mọ́;
9 Bí ìkùùkuu tí i túká, tí í sì fò lọ,
10 Kì yóò padà sínú ilé rẹ̀ mọ́,
11 “Nítorí náà èmi kì yóò pa ẹnu mi mọ́,
12 Èmi a máa ṣe Òkun tàbí ẹ̀mí búburú,
13 Nígbà tí mo wí pé, ibùsùn mi yóò tù mí lára,
14 Nígbà náà ni ìwọ fi àlá da yọ mi lénu bò mi,
15 Bẹ́ẹ̀ ni ọkàn mí yàn láti fún pa
16 O sú mi, èmi kò le wà títí:
17 “Kí ni ènìyàn tí ìwọ o máa kókìkí rẹ̀?
18 Àti ti ìwọ ó fi máa wá í bẹ̀ ẹ́ wò ni òròòwúrọ̀,
19 Yóò ti pẹ́ tó kí ìwọ kí ó tó fi mí sílẹ̀ lọ,
20 Èmi ti ṣẹ̀, ki ní èmi ó ṣe sí ọ.
21 Èéṣe tí ìwọ kò sì dárí ìrékọjá mi jìn,