1 Olúwa dá Jobu lóhùn sí pẹ̀lú, ó sì wí pé,
2 “Ẹni tí ń bá Olódùmarè wíjọ́ yóò ha kọ ní ẹ̀kọ́?
3 Nígbà náà ni Jobu dá Olúwa lóhùn wá ó sì wí pé,
4 “Kíyèsi i, ẹ̀gbin ni èmi—ohun kí ni èmi ó dà?
5 Ẹ̀ẹ̀kan ní mo sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n èmi kì yóò tún sọ mọ́;
6 Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àyíká wá, ó sì wí pé,
7 “Di àmùrè gírí ní ẹgbẹ́ rẹ bí ọkùnrin,
8 “Ìwọ ha fẹ́ mú ìdájọ́ mi di asán?
9 Ìwọ ni apá bí Ọlọ́run
10 Fi ọláńlá àti ọlá ìtayọ rẹ̀ ṣe ara rẹ ní ọ̀ṣọ́,
11 Mú ìrunú ìbínú rẹ jáde;
12 Wo gbogbo ìwà ìgbéraga, ènìyàn kí o sì rẹ ẹ sílẹ̀
13 Sin gbogbo wọn papọ̀ nínú erùpẹ̀,
14 Nígbà náà ní èmi ó yìn ọ́ pé,
15 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí kíyèsi Behemoti,
16 Wò o nísinsin yìí, agbára rẹ wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ,
17 Òun a máa jù ìrù rẹ̀ bí i igi kedari,
18 Egungun rẹ̀ ní ògùṣọ̀ idẹ,
19 Òun ni olórí nínú àwọn iṣẹ́ Ọlọ́run;
20 Nítòótọ́ òkè ńlá ńlá ní i mu ohun jíjẹ fún un wá,
21 Ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi lótusì,
22 Igi lótusì síji wọn bò o;
23 Kíyèsi i, odò ńlá sàn jọjọ, òun kò sálọ;
24 Ẹnìkan ha lè mú un ní ojú rẹ̀,