1 “Ìwọ mọ àkókò ìgbà tí àwọn ewúrẹ́ orí àpáta ń bímọ?
2 Ìwọ lè ka iye òṣùpá tí wọn ń pé,
3 Wọ́n tẹ ara wọn ba, wọ́n bímọ,
4 Àwọn ọmọ wọn rí dáradára, wọ́n dàgbà nínú ọ̀dàn;
5 “Ta ni ó jọ̀wọ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ oko lọ́wọ́?
6 èyí tí mo fi aginjù ṣe ilé fún,
7 Ó rẹ́rìn-ín sí ariwo ìlú,
8 Orí àtòlé òkè ńlá ni ibùjẹ oko rẹ̀,
9 “Àgbáǹréré ha jẹ́ sìn ọ́ bí?
10 Ìwọ le fi òkun tata de àgbáǹréré nínú aporo?
11 Ìwọ ó gbẹ́kẹ̀lé e nítorí agbára rẹ̀ pọ̀?
12 Ìwọ le gbẹ́kẹ̀lé pé, yóò mú èso oko rẹ̀ wá sílé,
13 “Ìwọ ni yóò ha fi ìyẹ́ dáradára fún ọ̀kín bí,
14 Ó yé ẹ̀yìn rẹ̀ sílẹ̀ lórí ilẹ̀,
15 tí ó sì gbàgbé pé, ẹsẹ̀ lè tẹ̀ wọ́n fọ́,
16 Kò ní àánú sí àwọn ọmọ rẹ̀ bí ẹni pé wọn kì í ṣe tirẹ̀;
17 nítorí pé Ọlọ́run kò fún un ní ọgbọ́n,
18 Nígbà tí ó gbé ara sókè,
19 “Ìwọ ni ó fi agbára fún ẹṣin bí,
20 Ìwọ le mú fò sókè bí ẹlẹ́ǹgà?
21 Ó fi ẹsẹ̀ halẹ̀ nínú àfonífojì, ó sì yọ̀ nínú agbára rẹ̀;
22 Ó fi ojú kékeré wo ẹ̀rù, àyà kò sì fò ó;
23 Lọ́dọ̀ rẹ ni apó-ọfà ń mì pẹkẹpẹkẹ,
24 Ó fi kíkorò ojú àti ìbínú ńlá gbé ilé mi,
25 Ó wí nígbà ìpè pé, Háà! Háà!
26 “Àwòdì ha máa ti ipa ọgbọ́n rẹ̀ fò sókè,
27 Idì ha máa fi àṣẹ rẹ̀ fò sókè,
28 Ó ń gbé, ó sì ń wò ní orí àpáta,
29 Láti ibẹ̀ lọ ni ó ti ń wá oúnjẹ kiri,
30 Àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú a máa mu ẹ̀jẹ̀,