1 “Ǹjẹ́ ìwọ le è fi ìwọ̀ fa Lefitani jáde?
2 Ìwọ lè fi okùn bọ̀ ọ́ ní í mú,
3 Òun ha jẹ́ bẹ ẹ̀bẹ̀ fún àánú lọ́dọ̀
4 Òun ha bá ọ dá májẹ̀mú bí?
5 Ìwọ ha lè ba sáré bí ẹni pé ẹyẹ ni,
6 Ẹgbẹ́ àwọn apẹja yóò ha máa tà á bí?
7 Ìwọ ha lè fi ọ̀kọ̀-irin gun awọ rẹ̀,
8 Fi ọwọ́ rẹ lé e lára,
9 Kíyèsi, ìgbìyànjú láti mú un ní asán;
10 Kò sí ẹni aláyà lílé tí ó lè ru sókè.
11 Ta ni ó kọ́kọ́ ṣe fún mi, tí èmi ìbá fi san án fún un?
12 “Èmi kì yóò fi ẹ̀yà ara Lefitani,
13 Ta ni yóò lè rídìí aṣọ àpáta rẹ̀?
14 Ta ni ó lè ṣí ìlẹ̀kùn iwájú rẹ̀?
15 Ìpẹ́ lílé ní ìgbéraga rẹ̀;
16 Èkínní fi ara mọ́ èkejì tó bẹ́ẹ̀
17 Èkínní fi ara mọ́ èkejì rẹ̀;
18 Nípa sí sin rẹ̀ ìmọ́lẹ̀ á mọ́,
19 Láti ẹnu rẹ ni ọ̀wọ́-iná ti jáde wá,
20 Láti ihò imú rẹ ni èéfín ti jáde wá,
21 Èémí rẹ̀ tiná bọ ẹ̀yin iná,
22 Ní ọrùn rẹ̀ ní agbára kù sí,
23 Jabajaba ẹran rẹ̀ dìjọ pọ̀,
24 Àyà rẹ̀ dúró gbagidi bí òkúta,
25 Nígbà tí ó bá gbé ara rẹ̀ sókè, àwọn alágbára bẹ̀rù;
26 Ọ̀kọ̀ tàbí idà, tàbí ọfà,
27 Ó ká irin sí ibi koríko gbígbẹ
28 Ọfà kò lè mú un sá;
29 Ó ka ẹṣin sí bí àgékù ìdì koríko;
30 Òkúta mímú ń bẹ nísàlẹ̀ abẹ́ rẹ̀,
31 Ó mú ibú omi hó bí ìkòkò;
32 Ó mú ipa ọ̀nà tan lẹ́yìn rẹ̀;
33 Lórí ilẹ̀ ayé kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ̀,
34 Ó bojú wo ohun gíga gbogbo,