1 Ìgbà náà ni Elifasi, ará Temani dáhùn wí pé,
2 “Bí àwa bá fi ẹnu lé e, láti bá ọ sọ̀rọ̀, ìwọ o ha banújẹ́?
3 Kíyèsi i, ìwọ sá ti kọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn,
4 Ọ̀rọ̀ rẹ ti gbé àwọn tí ń ṣubú lọ dúró,
5 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ó dé bá ọ, ó sì rẹ̀ ọ́, ó kọlù ọ́;
6 Ìbẹ̀rù Ọlọ́run rẹ kò ha jẹ́ ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ
7 “Èmi bẹ̀ ọ́ rántí, ta ni ó ṣègbé rí láìṣẹ̀?
8 Àní bí èmi ti rí i pé, àwọn tí ń ṣe ìtulẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀,
9 Nípa ìfẹ́ sí Ọlọ́run wọn a ṣègbé,
10 Bíbú ramúramù kìnnìún àti ohùn òǹrorò kìnnìún
11 Kìnnìún kígbe, nítorí àìrí ohun ọdẹ,
12 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí a fi ohun àṣírí kan hàn fún mi,
13 Ní ìrò inú lójú ìran òru,
14 Ẹ̀rù bà mí àti ìwárìrì
15 Nígbà náà ni ẹ̀mí kan kọjá lọ ní iwájú mi,
16 Ó dúró jẹ́ẹ́,
17 ‘Ẹni kíkú le jẹ́ olódodo ju Ọlọ́run,
18 Kíyèsi i, òun kò gbẹ́kẹ̀lé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀,
19 Mélòó mélòó àwọn tí ń gbé inú ilé amọ̀,
20 A pa wọ́n run láàrín òwúrọ̀ àti àṣálẹ́
21 A kò ha ké okùn iye wọ́n kúrò bí?