1 Ẹ̀yìn èyí ní Jobu yanu, ó sì fi ọjọ́ ìbí rẹ̀ ré
2 Jobu sọ, ó sì wí pé,
3 “Kí ọjọ́ tí a bí mi kí ó di ìgbàgbé,
4 Kí ọjọ́ náà kí ó já si òkùnkùn,
5 Kí òkùnkùn àti òjìji ikú fi ṣe ti ara wọn;
6 Kí òkùnkùn kí ó ṣú bo òru náà biribiri,
7 Kí òru náà kí ó yàgàn;
8 Kí àwọn tí í fi ọjọ́ gégùn ún kí o fi gégùn ún,
9 Kí ìràwọ̀ òwúrọ̀ ọjọ́ rẹ̀ kí ó ṣókùnkùn;
10 nítorí tí kò sé ìlẹ̀kùn inú ìyá mi,
11 “Èéṣe tí èmi kò fi kú láti inú wá,
12 Èéṣe tí orúnkún wá pàdé mi,
13 Ǹjẹ́ nísinsin yìí èmi ìbá ti dùbúlẹ̀ jẹ́ẹ́;
14 pẹ̀lú àwọn ọba àti ìgbìmọ̀ ayé
15 Tàbí pẹ̀lú àwọn ọmọ-aládé
16 Tàbí bí ọlẹ̀ tí a sin, èmi kì bá ti sí:
17 Níbẹ̀ ni ẹni búburú ṣíwọ́ ìyọnilẹ́nu,
18 Níbẹ̀ ni àwọn ìgbèkùn sinmi pọ̀,
19 Àti èwe àti àgbà wà níbẹ̀,
20 “Nítorí kí ni a ṣe fi ìmọ́lẹ̀ fún òtòṣì,
21 tí wọ́n dúró de ikú, ṣùgbọ́n òun kò wá,
22 Ẹni tí ó yọ̀ gidigidi,
23 Kí ni a fi ìmọ́lẹ̀ fún ẹni
24 Nítorí pé èémí-ẹ̀dùn wà ṣáájú oúnjẹ mi;
25 Nítorí pé ohun náà tí mo bẹ̀rù gidigidi ni ó dé bá mi yìí,
26 Èmi wà láìní àlàáfíà, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò ní ìsinmi;