1 “Wò ó, ojú mi ti rí gbogbo èyí rí,
2 Ohun tí ẹ̀yin mọ̀, èmi mọ̀ pẹ̀lú,
3 Nítòótọ́ èmi ó bá Olódùmarè sọ̀rọ̀,
4 Ẹ̀yin fi irọ́ bá mi sọ̀rọ̀,
5 Háà! ẹ̀yin kì bá kúkú dákẹ́!
6 Ẹ gbọ́ àwíyé mi nísinsin yìí;
7 Ẹ̀yin fẹ́ sọ ìsọkúsọ fún Ọlọ́run?
8 Ẹ̀yin fẹ́ ṣe ojúsàájú rẹ̀?
9 Ó ha dára to tí yóò hú àṣírí yín síta,
10 Yóò máa bá yín wí nítòótọ́,
11 Ìwà ọlá rẹ̀ kì yóò bà yín lẹ́rù bí?
12 Àwọn òwe yín dàbí eérú,
13 “Ẹ pa ẹnu yín mọ́ kúrò lára mi, kí èmi kí ó lè sọ̀rọ̀,
14 Ǹjẹ́ nítorí kí ni èmi ṣe ń fi eyín mi bu ẹran-ara mi jẹ,
15 Bí ó tilẹ̀ pa mí, síbẹ̀ èmi ó máa gbẹ́kẹ̀lé e,
16 Èyí ni yóò sì ṣe ìgbàlà mi,
17 Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹnu mi ní ìfarabalẹ̀,
18 Wò ó nísinsin yìí, èmi ti mura ọ̀ràn mi sílẹ̀;
19 Ta ni òun ti yóò bá mi ṣàròyé?
20 “Ṣùgbọ́n, má ṣe ṣe ohun méjì yìí sí mi,
21 Fa ọwọ́ rẹ sẹ́yìn kúrò lára mi,
22 Nígbà náà ni kí ìwọ kí ó pè, èmi o sì dáhùn,
23 Mélòó ní àìṣedéédéé àti ẹ̀ṣẹ̀ mi?
24 Nítorí kí ni ìwọ ṣe pa ojú rẹ mọ́,
25 Ìwọ ó fa ewé ti afẹ́fẹ́ ń fẹ́ síyìn-ín sọ́hùn-ún ya bi?
26 Nítorí pé ìwọ kọ̀wé ohun kíkorò sí mi,
27 Ìwọ kàn àbà mọ́ mi lẹ́sẹ̀ pẹ̀lú,
28 “Bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn ń ṣègbé bí ohun ìdíbàjẹ́,