1 Jobu sì dáhùn, ó sì wí pé,
2 “Kò sí àní àní níbẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ni àwọn ènìyàn náà,
3 Ṣùgbọ́n èmi ní ìyè nínú gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin;
4 “Èmi dàbí ẹni tí a ń fi ṣe ẹlẹ́yà lọ́dọ̀ aládùúgbò rẹ̀,
5 Ó rọrùn fún ènìyàn láti fi ìbànújẹ́ ẹlòmíràn ṣe ẹlẹ́yà
6 Àgọ́ àwọn ìgárá ọlọ́ṣà wá láìní ìbẹ̀rù;
7 “Ṣùgbọ́n nísinsin yìí bí àwọn ẹranko léèrè, wọn o kọ́ ọ ní ẹ̀kọ́,
8 Tàbí ba ilẹ̀ ayé sọ̀rọ̀, yóò sì kọ́ ọ,
9 Ta ni kò mọ̀ nínú gbogbo nǹkan wọ̀nyí pé,
10 Ní ọwọ́ ẹni tí ẹ̀mí ohun alààyè gbogbo gbé wà,
11 Etí kì í dán ọ̀rọ̀ wò bí
12 Àwọn arúgbó ni ọgbọ́n wà fún,
13 “Ti Ọlọ́run ni ọgbọ́n àti agbára;
14 Kíyèsi i, ó bì wó, a kò sì lè gbe ró mọ́;
15 Kíyèsi i, ó dá àwọn omi dúró, wọ́n sì gbẹ;
16 Tìrẹ ni agbára àti ìṣẹ́gun;
17 Ó mú àwọn ìgbìmọ̀ lọ ní ìhòhò
18 Ó tú ìdè ọba
19 Ó mú àwọn àlùfáà lọ ní ìhòhò
20 Ó mú ọ̀rọ̀ ẹnu ẹni ìgbẹ́kẹ̀lé kúrò
21 Ó bu ẹ̀gàn lu àwọn ọmọ ọlọ́lá
22 Ó hú ìdí ohun ìjìnlẹ̀ jáde láti inú òkùnkùn wá
23 Òun a mú orílẹ̀-èdè bí sí i, a sì run wọ́n;
24 Òun a gba òye àwọn olórí àwọn ènìyàn aráyé,
25 Wọn a máa fi ọwọ́ ta ilẹ̀ nínú òkùnkùn níbi tí kò sí ìmọ́lẹ̀;