1 Ta ni ó ti gba ìròyìn in wa gbọ́
2 Òun dàgbàsókè níwájú rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àṣẹ̀ṣẹ̀yọ irúgbìn,
3 A kẹ́gàn rẹ̀ àwọn ènìyàn sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀,
4 Lóòtítọ́ ó ti ru àìlera wa lọ
5 Ṣùgbọ́n a sá a lọ́gbẹ́ nítorí àìṣedéédéé wa
6 Gbogbo wa bí àgùntàn, ti ṣìnà lọ,
7 A jẹ ẹ́ ní yà, a sì pọ́n ọn lójú,
8 Pẹ̀lú ìpọ́nlójú àti ìdánilẹ́jọ́ ni a mú un jáde lọ,
9 A fún un ní ibojì pẹ̀lú àwọn ìkà,
10 Síbẹ̀, ó wu Olúwa láti pa á lára
11 Lẹ́yìn ìpọ́njú ẹ̀mí rẹ̀,
12 Nítorí náà èmi yóò fún un ní ìpín pẹ̀lú àwọn ẹni ńlá