1 Wò ó, ọba kan yóò jẹ nínú òdodo
2 Ẹnìkọ̀ọ̀kan yóò jẹ́ bí ibi ìṣápamọ́ kúrò lọ́wọ́ afẹ́fẹ́
3 Nígbà náà ni ojú àwọn tí ó rí kò ní padé mọ́,
4 Ọkàn àwọn oníwàdùwàdù ni yóò là tí yóò sì yè,
5 A kò ní pe òmùgọ̀ ní ọlọ́lá mọ́
6 Nítorí òmùgọ̀ sọ̀rọ̀ òmùgọ̀,
7 Ibi ni gbogbo ọgbọ́n àwọn ìkà ènìyàn jẹ́,
8 Ṣùgbọ́n ọlọ́lá ènìyàn a máa pète ohun ńlá
9 Ẹ̀yin obìnrin tí ẹ ti gba ìtẹ́lọ́rùn gidi
10 Ní ó lé díẹ̀ ní ọdún kan
11 Wárìrì, ẹ̀yin obìnrin onítẹ̀lọ́rùn;
12 Ẹ lu ọmú yín fún pápá ìgbádùn náà,
13 àti fún ilẹ̀ àwọn ènìyàn mi,
14 Ilé olódi ni a ó kọ̀sílẹ̀,
15 títí a ó fi tú Ẹ̀mí sí wa lórí láti òkè wá,
16 Ẹ̀tọ́ yóò máa gbé ní inú aṣálẹ̀
17 Èso òdodo náà yóò sì jẹ́ àlàáfíà;
18 Àwọn ènìyàn mi yóò máa gbé ní ibùgbé àlàáfíà,
19 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé yìnyín ti tẹ́jú igbó pẹrẹsẹ
20 báwo ni ẹ ó ti jẹ́ alábùkún tó,