1 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó jẹ mọ́ àfonífojì ìran.
2 Ìwọ ìlú tí ó kún fún rúkèrúdò,
3 Gbogbo àwọn olórí i yín ti jùmọ̀ sálọ;
4 Nítorí náà ni mo wí pé, “Yípadà kúrò lọ́dọ̀ mi:
5 Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ọjọ́ kan
6 Elamu mú apó-ọfà lọ́wọ́,
7 Àyànfẹ́ àfonífojì rẹ kún fún kẹ̀kẹ́ ogun,
8 Gbogbo ààbò Juda ni a ti ká kúrò.
9 Ìwọ rí i pé ìlú u Dafidi
10 Ìwọ ka àwọn ilé tí ó wà ní Jerusalẹmu
11 Ìwọ mọ agbemi sí àárín ògiri méjì
12 Olúwa, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun,
13 Ṣùgbọ́n wò ó, ayọ̀ àti ayẹyẹ wà;
14 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti sọ èyí di mí mọ̀ létí ì mi: “Títí di ọjọ́ ikú yín a kò ní ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ yìí,” ni Olúwa wí, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
15 Èyí ni ohun tí Olúwa, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí,
16 Kí ni ohun tí ò ń ṣe níhìn-ín yìí àti pé
17 “Kíyèsára, Olúwa fẹ́ gbá ọ mú gírígírí
18 Òun yóò ká ọ rúgúdù bí i òkìtì
19 Èmi yóò yọ ọ́ kúrò ní ipò rẹ,
20 “Ní ọjọ́ náà. Èmi yóò ké sí ọmọ ọ̀dọ̀ mi, Eliakimu ọmọ Hilkiah.
21 Èmi yóò fi aṣọ rẹ wọ̀ ọ́, n ó sì so ẹ̀wọ̀n rẹ mọ́ ọn ní ọrùn, èmi ó sì gbé àṣẹ rẹ lé e lọ́wọ́. Òun yó sì jẹ́ baba fún gbogbo olùgbé e Jerusalẹmu àti fún ilé e Juda.
22 Èmi yóò sì fi kọ́kọ́rọ́ ilé e Dafidi lé e ní èjìká; ohunkóhun tí ó bá ṣí, ẹnikẹ́ni kì yóò lè ti, ohunkóhun tí ó bá sì tì, ẹnikẹ́ni kì yóò le è ṣí.
23 Èmi yóò sì kàn mọ́lẹ̀ bí èèkàn tí ó dúró gírígírí ní ààyè e rẹ̀; òun yóò sì jẹ́ ibùjókòó ọlá fún ilé baba rẹ̀.
24 Gbogbo ògo ìdílé rẹ̀ ni wọn yóò sì fi kọ ní ọrùn: ìran rẹ̀ àti àrọ́mọdọ́mọ rẹ̀, gbogbo ohun èlò ife, títí dé orí ago ọtí.
25 “Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Èèkàn tí a kàn mọ́lẹ̀ gírígírí ní ààyè e rẹ̀ yóò yẹrí, yóò dẹ̀gbẹ́ yóò sì fẹ̀gbẹ́ lélẹ̀ àti ẹrù tí ó létéńté lórí i rẹ̀ ni a ó gé lulẹ̀.” Olúwa ni ó ti sọ ọ́.