1 Olúwa, Ọlọ́run tí ó gbà mí là,
2 Jẹ́ kí àdúrà mi kí ó wá sí iwájú rẹ;
3 Nítorí ọkàn mi kún fún ìpọ́njú
4 A kà mí mọ́ àwọn tí wọ́n lọ sí ọ̀gbun ilẹ̀
5 A yà mí sọ́tọ̀ pẹ̀lú àwọn òkú
6 Ìwọ tí ó fi mí sí kòtò jíjìn,
7 Ìbínú rẹ ṣubú lé mi gidigidi;
8 Ìwọ tí gba ọ̀rẹ́ mi tí ó súnmọ́ mi kúrò lọ́wọ́ mi
9 ojú mi káàánú nítorí ìpọ́njú.
10 Ìwọ ó fi iṣẹ́ ìyanu rẹ hàn fún òkú bi?
11 A ó ha fi ìṣeun ìfẹ́ rẹ hàn ní ibojì bí,
12 A ha lè mọ iṣẹ́ ìyanu rẹ ní òkùnkùn bí
13 Ṣùgbọ́n mo kígbe sí ọ fún ìrànlọ́wọ́, Olúwa;
14 Olúwa, èéṣe tí ìwọ fi kọ̀ mí
15 Láti ìgbà èwe mi, ìṣẹ́ ń ṣẹ́ mi,
16 Ìbínú rẹ ti kọjá lára mi;
17 Ní gbogbo ọjọ́ ni wọn yí mi ká bí ìkún omi;
18 Ìwọ ti mú ọ̀rẹ́ àti olùfẹ́ mi kúrò lọ́dọ̀ mi;