1 Gbọ́ ẹkún mi, Ọlọ́run;
2 Láti òpin ayé wá ni èmi yóò pè ọ́,
3 Nítorí ìwọ ti jẹ́ ibi ààbò mi,
4 Mo ń lépa láti máa gbé nínú àgọ́ rẹ títí láé
5 Nítorí ìwọ ti gbọ́ àwọn ẹ̀jẹ́ mi, Ọlọ́run;
6 Jẹ́ kí ẹ̀mí ọba kí ó gùn,
7 Kí ó máa jẹ ọba níwájú Ọlọ́run títí láé;
8 Nígbà náà ni èmi ó máa kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ títí láé