1 Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.
2 Jẹ́ kí Israẹli kí ó ní inú dídùn sí ẹni tí ó dá a
3 Jẹ́ kí wọn kí ó fi ijó yin orúkọ rẹ̀
4 Nítorí Olúwa ní inú dídùn sí àwọn ènìyàn rẹ̀
5 Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mímọ́ kí ó yọ̀ nínú ọlá rẹ̀
6 Kí ìyìn Ọlọ́run kí ó wà ní ẹnu wọn
7 Láti gba ẹ̀san lára àwọn orílẹ̀-èdè,
8 láti fi ẹ̀wọ̀n de àwọn ọba wọn
9 Láti ṣe ìdájọ́ tí àkọsílẹ̀ rẹ̀ sí wọn