1 Olúwa, ìwọ tí wádìí mi,
2 Ìwọ mọ̀ ìjókòó mi àti ìdìde mi,
3 Ìwọ yí ipa ọ̀nà mi ká àti ìdùbúlẹ̀ mi,
4 Nítorí tí kò sí ọ̀rọ̀ kan ní ahọ́n mi,
5 Ìwọ sé mi mọ́ lẹ́yìn àti níwájú,
6 Irú ìmọ̀ yìí jẹ ohun ìyanu fún mi jù;
7 Níbo ní èmi yóò gbé lọ kúrò ni ọwọ́ ẹ̀mí rẹ?
8 Bí èmi bá gòkè lọ sí ọ̀run, ìwọ wà níbẹ̀;
9 Èmi ìbá mú ìyẹ́ apá òwúrọ̀,
10 àní, níbẹ̀ náà ni ọwọ́ rẹ̀ yóò fà mí
11 Bí mo bá wí pé, “Ǹjẹ́ kí òkùnkùn kí ó bò mí mọ́lẹ̀;
12 Nítòótọ́ òkùnkùn kì í ṣú lọ́dọ̀ rẹ;
13 Nítorí ìwọ ni ó dá ọkàn mi;
14 Èmi yóò yìn ọ, nítorí tẹ̀rù tẹ̀rù àti tìyanu tìyanu ní a dá mi;
15 Ẹ̀dá ara mi kò pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ rẹ,
16 ojú rẹ ti rí ohun ara mi
17 Ọlọ́run, èrò inú rẹ tí ṣe iyebíye tó fún mi,
18 Èmi ìbá kà wọ́n,
19 Ọlọ́run ìbá jẹ́ pa àwọn ènìyàn búburú nítòótọ́;
20 Ẹni tí ń fi inú búburú sọ̀rọ̀ sí ọ,
21 Olúwa, ǹjẹ́ èmi kò kórìíra àwọn tó kórìíra rẹ?
22 Èmi kórìíra wọn ní àkótán;
23 Ọlọ́run, wádìí mi, kí o sì mọ ọkàn mí;
24 Kí ó sì wò ó bí ipa ọ̀nà búburú