1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó dára;
2 Jẹ́ kí Israẹli wí pé:
3 Jẹ́ kí ilé Aaroni wí pé:
4 Jẹ́ kí àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa wí pé:
5 Nínú ìrora mi, mo sọkún sí Olúwa,
6 Olúwa ń bẹ fún èmi; èmi kì yóò bẹ̀rù.
7 Olúwa ń bẹ fún mi; òun ni olùrànlọ́wọ́ mi.
8 Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa
9 Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa
10 Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yí mi káàkiri,
11 Wọ́n yí mi káàkiri ní gbogbo ẹ̀gbẹ́,
12 Wọ́n gbá yìn ìn yí mi ká bí oyin,
13 Ìwọ tì mí gidigidi kí n lè ṣubú,
14 Olúwa ni agbára àti orin mi;
15 Ohùn ayọ̀ àti ìgbàlà ń bẹ nínú àgọ́ àwọn olódodo:
16 Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ní a gbéga;
17 Èmi kì yóò kú, ṣùgbọ́n èmi yóò yè,
18 Olúwa bá mi wí gidigidi,
19 Ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òdodo fún mi:
20 Èyí ni ìlẹ̀kùn Olúwa
21 Èmi yóò fi ọpẹ́ fún ọ, nítorí ó dá mi lóhùn;
22 Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀,
23 Olúwa ti ṣe èyí,
24 Èyí ni ọjọ́ tí Olúwa dá:
25 Olúwa, gbà wá;
26 Ìbùkún ni ẹni tí ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa.
27 Olúwa ni Ọlọ́run,
28 Ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò máa fi ọpẹ́ fún ọ;
29 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun;