1 Ọlọ́run, ti èmi ń fi ìyìn fún,
2 nítorí àwọn ènìyàn búburú àti ẹlẹ́tàn
3 Wọ́n fi ọ̀rọ̀ ìríra yí mi káàkiri;
4 Nípò ìfẹ́ mi, wọn ń ṣe ọ̀tá mi,
5 Wọ́n sì fi ibi san ìre fún mi
6 Yan àwọn ènìyàn búburú láti dojúkọ
7 Kí a dá a lẹ́bi nígbà tí a bá ṣe ìdájọ́
8 Kí ọjọ́ rẹ̀ kí ó kúrú;
9 Kí àwọn ọmọ rẹ̀ di aláìní baba
10 Jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ máa ṣagbe kiri
11 Jẹ́ kí alọ́nilọ́wọ́gbà kí ó mú ohun gbogbo tí ó ní
12 Má ṣe jẹ́ kí ẹnìkan ṣe àánú fún un
13 Kí a gé àrọ́mọdọ́mọ rẹ̀ kúrò
14 Kí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba rẹ̀ kí
15 Jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ wọn kí ó wà ní ìrántí níwájú Olúwa
16 Nítorí kò rántí láti ṣàánú,
17 Ó fẹ́ràn láti máa mú ègún wá sí orí rẹ̀:
18 Bí ó ti fi ègún wọ ará rẹ̀ láṣọ bí ẹ̀wù
19 Jẹ́ kí ó rí fún un bí aṣọ tí a dà bò ó ní ara,
20 Èyí ni èrè àwọn ọ̀tá mi láti ọwọ́ Olúwa wá;
21 Ṣùgbọ́n ìwọ, ìwọ ṣe fún mi Olúwa Olódùmarè,
22 Nítorí pé tálákà àti aláìní ni mí,
23 Èmi ń kọjá lọ bí òjìji tí àṣálẹ́,
24 Eékún mi di aláìlera nítorí àwẹ̀ gbígbà
25 Mo dàbí ẹ̀gàn fún àwọn olùfisùn mi;
26 Ràn mí lọ́wọ́, Olúwa Ọlọ́run mi;
27 Jẹ́ kí wọn mọ̀ pé ọwọ́ rẹ ni èyí
28 Wọ́n ó máa gégùn ún, ṣùgbọ́n ìwọ máa súre,
29 Jẹ́ kí a wọ àwọn ọ̀tá mi ní aṣọ ìtìjú
30 Pẹ̀lú ẹnu mi èmi yóò máa yin Olúwa gidigidi
31 Nítorí ó dúró ní apá ọ̀tún aláìní