1 Gbọ́ àdúrà mi, Olúwa,
2 Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ kúrò lọ́dọ̀ mi
3 Nítorí tí ọjọ́ mi run bí èéfín;
4 Àyà mi lù, ó sì rọ bí i koríko;
5 Nítorí ohùn ìkérora mi,
6 Èmi dàbí ẹyẹ igún ní ijù:
7 Èmi dìde; èmi dàbí ẹyẹ lórí ilé.
8 Ní ọjọ́ gbogbo, àwọn ọ̀tá ológoṣẹ́ mi ń gàn mí;
9 Èmi jẹ eérú gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ mi, èmi sì da ohun mímu mi pọ̀ pẹ̀lú omijé.
10 Nítorí ìbínú ríru rẹ, nítorí ìwọ ti gbé mi sókè, ìwọ sì gbé mi ṣánlẹ̀.
11 Ọjọ́ mi dàbí òjìji àṣálẹ́
12 Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, ni yóò dúró láéláé;
13 Ìwọ ó dìde ìwọ ó sì ṣàánú fún Sioni,
14 Nítorí tí àwọn òkúta jẹ́ inú dídùn sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ;
15 Àwọn kèfèrí yóò bẹ̀rù orúkọ Olúwa,
16 Torí tí Olúwa yóò gbé Sioni ró, yóò farahàn nínú ògo rẹ̀.
17 Yóò dáhùn àdúrà àwọn aláìní;
18 Jẹ́ kí a kọ èyí fún ìran tí ń bọ̀,
19 “Olúwa wo ilẹ̀ láti òkè mímọ́ rẹ̀ wá
20 láti gbọ́ ìrora ará túbú,
21 Kí a lè sọ orúkọ Olúwa ní Sioni
22 Ní ìgbà tí a kó àwọn ènìyàn àti
23 Ní ipa ọ̀nà mi, ó rẹ agbára mi sílẹ̀,
24 Èmi sì wí pé:
25 Ní ìbẹ̀rẹ̀ ní ìwọ fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀,
26 Wọn yóò ṣègbé, wọn yóò parun, ṣùgbọ́n ìwọ yóò wà;
27 Ṣùgbọ́n ìwọ wà digbí síbẹ̀,
28 Àwọn ọmọ ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò dúró ní iwájú rẹ pẹ́;