1 Àwọn ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ ti Lemueli ọba, ọ̀rọ̀ ẹ̀kọ́ tí ìyá rẹ̀ kọ́ ọ,
2 “Gbọ́ ìwọ ọmọ mi, gbọ́ ìwọ ọmọ inú mi!
3 Má ṣe lo agbára rẹ lórí obìnrin,
4 “Kì í ṣe fún àwọn ọba, ìwọ Lemueli,
5 kí wọn má ba à mu ọtí yó kí wọn sì gbàgbé ohun tí òfin wí,
6 Fi ọtí líle fún àwọn tí ń ṣègbé
7 Jẹ́ kí wọn mu ọtí kí wọn sì gbàgbé òsì wọn
8 “Sọ̀rọ̀ lórúkọ àwọn tí kò le sọ̀rọ̀ fúnra wọn
9 Sọ̀rọ̀ kí o sì ṣe ìdájọ́ àìṣègbè
10 Ta ni ó le rí aya oníwà rere?
11 Ọkọ rẹ̀ ní ìgbẹ́kẹ̀lé púpọ̀ nínú rẹ̀
12 Ire ní ó ń ṣe fún un, kì í ṣe ibi
13 Ó sa aṣọ irun àgùntàn olówùú àti ọ̀gbọ̀
14 Ó dàbí ọkọ̀ ojú omi tí àwọn oníṣòwò;
15 Ó dìde nígbà tí òkùnkùn sì kùn;
16 Ó kíyèsi oko kan, ó sì rà á;
17 Ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rẹ̀ tagbára tagbára
18 Ó rí i pé òwò òun pé
19 Ní ọwọ́ rẹ̀, ó di kẹ̀kẹ́ òwú mú
20 O la ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn tálákà
21 Nígbà tí òjò-dídì rọ̀, kò bẹ̀rù nítorí ìdílé rẹ̀
22 Ó ṣe aṣọ títẹ́ fún ibùsùn rẹ̀;
23 A bọ̀wọ̀ fún ọkọ rẹ̀ ní ẹnu ibodè ìlú
24 Ó ń ṣe àwọn aṣọ dáradára ó sì ń tà wọ́n
25 Agbára àti ọlá ni ó wò ọ́ láṣọ
26 A sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ọgbọ́n
27 Ó ń bojútó gbogbo ètò ilé rẹ̀
28 Àwọn ọmọ rẹ̀ dìde wọ́n sì pè é ní alábùkún
29 “Ọ̀pọ̀lọpọ̀ obìnrin ní ń ṣe nǹkan ọlọ́lá
30 Ojú dáradára a máa tan ni, ẹwà sì jẹ́ asán
31 Sì fún un ní èrè tí ó tọ́ sí i