1 Yíyan orúkọ rere sàn ju púpọ̀ ọrọ̀ lọ,
2 Ọlọ́rọ̀ àti tálákà péjọpọ̀:
3 Ọlọ́gbọ́n ènìyàn ti rí ibi tẹ́lẹ̀,
4 Èrè ìrẹ̀lẹ̀ àti ìbẹ̀rù Olúwa ni ọrọ̀ ọlá, àti ìyè.
5 Ègún àti ìdẹ̀kùn ń bẹ ní ọ̀nà aláyídáyidà:
6 Tọ́ ọmọdé ní ọ̀nà tí yóò tọ̀:
7 Ọlọ́rọ̀ ṣe olórí olùpọ́njú,
8 Ẹni tí ó bá fúnrúgbìn ẹ̀ṣẹ̀, yóò ká asán:
9 Ẹni tí ó ní ojú àánú ni a ó bùkún fún;
10 Lé ẹlẹ́gàn sí ìta, ìjà yóò sì jáde;
11 Ẹni tí ó fẹ́ ìwà funfun ti àyà,
12 Ojú Olúwa pa ìmọ̀ mọ́,
13 Ọ̀lẹ wí pé, “Kìnnìún ń bẹ lóde!
14 Ẹnu àwọn àjèjì obìnrin, ihò jíjìn ni;
15 Àyà ọmọdé ni ìwà wèrè dì sí;
16 Ẹni tó ń ni tálákà lára láti ní ọrọ̀,
17 Dẹtí rẹ sílẹ̀,
18 Nítorí ohun dídùn ni bí ìwọ bá pa wọ́n mọ́ ní inú rẹ;
19 Kí ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ lè wà ní ti Olúwa,
20 Èmi kò ha ti kọ̀wé ohun dáradára
21 kí ó lè mú ọ mọ ìdájú ọ̀rọ̀ òtítọ́;
22 Má ṣe ja tálákà ní olè, nítorí tí ó jẹ́ tálákà:
23 nítorí Olúwa yóò gbèjà wọn,
24 Má ṣe bá oníbìínú ènìyàn ṣe ọ̀rẹ́;
25 Kí ìwọ má ba à kọ́ ìwà rẹ̀, ìwọ a sì gba ìkẹ́kùn fún ara rẹ.
26 Má ṣe wà nínú àwọn tí ń ṣe ìgbọ̀nwọ́,
27 Bí ìwọ kò bá ní nǹkan tí ìwọ ó fi san,
28 Má ṣe yẹ ààlà ilẹ̀ ìgbàanì,
29 Ìwọ ha rí ènìyàn tí ó ń fi àìṣe ìmẹ́lẹ́ ṣe iṣẹ́ rẹ̀?