1 Ènìyàn tí kò ba ni rẹ́ a máa lépa ìmọ̀ ara rẹ̀;
2 Aláìgbọ́n kò rí inú dídùn sí òye
3 Nígbà ti ènìyàn búburú dé ni ẹ̀gàn dé,
4 Ọ̀rọ̀ ẹnu ènìyàn jẹ́ omi jíjìn,
5 Kò dára kí ènìyàn ṣe ojúsàájú fún ènìyàn búburú
6 Ètè aláìgbọ́n dá ìjà sílẹ̀
7 Ẹnu aláìgbọ́n ni ó ba tirẹ̀ jẹ́,
8 Ọ̀rọ̀ olófòófó dàbí oúnjẹ àdídùn;
9 Ẹni tí kò ṣe déédé nínú iṣẹ́ rẹ̀
10 Orúkọ Olúwa, ilé ìṣọ́ agbára ni;
11 Ọ̀rọ̀ olówó ni ìlú olódi wọn;
12 Ṣáájú ìṣubú ọkàn ènìyàn a kọ́kọ́ máa gbéraga,
13 Ẹni tí ó ń fèsì kí ó tó gbọ́,
14 Ọkàn ènìyàn a máa gbé e ró nígbà àìsàn,
15 Ọkàn olóye ní i gba ìmọ̀;
16 Ẹ̀bùn máa ń ṣí ọ̀nà fún ẹni tí ń fún ni lẹ́bùn
17 Ẹni tí ó kọ́kọ́ rọjọ́ máa ń dàbí i pé ó jàre,
18 Ìbò dídì máa ń parí ìjà
19 Arákùnrin tí a ṣẹ̀ sí ṣòro yípadà ju ìlú olódi lọ,
20 Láti inú èso ẹnu rẹ̀ ikùn ènìyàn a yó;
21 Ikú àti ìyè ń bẹ nípa ahọ́n wọn,
22 Ẹni tí ó rí aya fẹ́, rí ohun rere,
23 Tálákà ń bẹ̀bẹ̀ fún àánú,
24 Ènìyàn tí ó ní ọ̀rẹ́ púpọ̀ le è parun,