1 Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Jeremiah wòlíì wá nípa àwọn Orílẹ̀-èdè.
2 Nípa Ejibiti.
3 “Ẹ múra àpáta, èyí tí ó tóbi, àti èyí tí ó kéré,
4 Ẹ di ẹṣin ní gàárì,
5 Kí ni nǹkan tí mo tún rí?
6 “Ẹni tí ó yára kì yóò le sálọ,
7 “Ta ni èyí tí ó gòkè wá bí odò Ejibiti,
8 Ejibiti dìde bí odò náà,
9 Ẹ gòkè wá ẹ̀yin ẹṣin,
10 Ṣùgbọ́n ọjọ́ náà jẹ́ ti Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun,
11 “Gòkè lọ sí Gileadi, kí o sì mú ìkunra,
12 Àwọn orílẹ̀-èdè yóò gbọ́ nípa ìtìjú rẹ,
13 Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó bá Jeremiah wòlíì nì sọ nípa wíwá Nebukadnessari ọba Babeli láti lọ dojú ìjà kọ Ejibiti:
14 “Kéde èyí ní Ejibiti, sì sọ ọ́ ní Migdoli,
15 Èéṣe tí àwọn akọni rẹ fi ṣubú?
16 Wọn yóò máa ṣubú léraléra
17 Níbẹ̀ ni wọn ó kígbe pé,
18 “Bí èmi ti wà láààyè,” ni ọba,
19 Ìwọ, ọmọbìnrin ti ń gbé Ejibiti
20 “Ẹgbọrọ abo màlúù tó lẹ́wà ní Ejibiti
21 Àwọn jagunjagun rẹ̀
22 Ejibiti yóò pòṣé bí ejò tí ń sá
23 Wọn o gé igbó rẹ̀ lulẹ̀,” ni Olúwa wí,
24 A ó dójútì ọmọbìnrin Ejibiti,
25 Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí pé: “Èmi yóò rọ̀jò ìyà mi sórí Amoni òrìṣà Tebesi, sórí Farao, sórí Ejibiti àti àwọn òrìṣà rẹ̀ àti sórí àwọn ọba rẹ̀ àti sórí àwọn tó gbẹ́kẹ̀lé Farao.
26 Èmi ó sì fi wọ́n lé àwọn tó wá ẹ̀mí wọn lọ́wọ́, lé Nebukadnessari ọba Babeli, ṣùgbọ́n lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, Ejibiti yóò sì di gbígbé bí i ti àtijọ́,” ni Olúwa wí.
27 “Má bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu ìránṣẹ́ mi,
28 Má bẹ̀rù, Jakọbu ìránṣẹ́ mi,