Jeremias 31

YOR

1 “Nígbà náà, Èmi yóò jẹ́ Ọlọ́run fún gbogbo ìdílé ìran Israẹli, àwọn náà yóò sì jẹ́ ènìyàn mi,” ni Olúwa wí.

2 Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

3 Olúwa ti fi ara rẹ̀ hàn wá ní ìgbà kan rí, ó wí pé:

4 Èmi yóò tún gbé e yín sókè,

5 Ẹ ó tún gbin ọgbà àjàrà

6 Ọjọ́ kan máa wà tí àwọn olùṣọ́ yóò kígbe jáde

7 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ wí pé:

8 Wò ó, Èmi yóò mú wọn wá láti ilẹ̀ àríwá;

9 Wọn yóò wá pẹ̀lú ẹkún,

10 “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin orílẹ̀-èdè

11 Nítorí Olúwa ti tú Jakọbu sílẹ̀, o sì rà á padà

12 Wọn yóò wá, wọn ó sì hó ìhó ayọ̀ lórí òkè Sioni;

13 Àwọn wúńdíá yóò jó, wọn ó sì kún fún ayọ̀,

14 Èmi ó tẹ́ àwọn àlùfáà lọ́rùn pẹ̀lú ọ̀pọ̀;

15 Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

16 Báyìí ni Olúwa wí:

17 Nítorí ìrètí wà fún ọjọ́ iwájú rẹ,”

18 “Nítòótọ́, èmi ti gbọ́ ìpohùnréré Efraimu wí pé,

19 Lẹ́yìn tí èmi ti yípadà,

20 Efraimu kì í ha í ṣe ọmọkùnrin mi dáradára

21 “Gbé àmì ojú ọ̀nà dìde,

22 Ìwọ yóò ti ṣìnà pẹ́ tó,

23 Báyìí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí: “Nígbà tí èmi bá kó wọn dé láti ìgbèkùn; àwọn ènìyàn tí ó wà ní ilẹ̀ Juda àti ní àwọn ìlú rẹ̀ yóò tún lo àwọn ọ̀rọ̀ yìí lẹ́ẹ̀kan sí i; wí pé, ‘Kí Olúwa kí ó bùkún fún ọ, ìwọ ibùgbé òdodo, ìwọ òkè ìwà mímọ́.’

24 Àwọn ènìyàn yóò gbé papọ̀ ní Juda àti ní gbogbo àwọn ìlú rẹ̀; bákan náà ni àgbẹ̀ àti àwọn tí ń tẹ̀lé agbo ẹran wọn ká.

25 Èmi yóò sọ aláàárẹ̀ di ọ̀tun, èmi yóò sì tẹ́ gbogbo ọkàn tí ń káàánú lọ́rùn.”

26 Lórí èyí ni mo jí, mo sì wò yíká, oorun mi sì dùn mọ́ mi.

27 “Wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “nígbà tí èmi yóò gbin ilé Israẹli àti ilé Juda pẹ̀lú irúgbìn ọmọ ènìyàn àti ẹranko.

28 Gẹ́gẹ́ bí mo ṣe ń ṣọ́ wọn, láti fàtu, àti láti wó lulẹ̀, àti láti gba ìṣàkóso, láti bàjẹ́ àti láti mú ibi wá, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣọ́ wọn láti kọ́ àti láti gbìn,” ni Olúwa wí.

29 “Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ènìyàn kò ní sọ mọ́ pé:

30 Ṣùgbọ́n olúkúlùkù ni yóò kú fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ èso kíkan ni eyín yóò kan.

31 “Ìgbà kan ń bọ̀,” ni Olúwa wí,

32 Kò ní dàbí májẹ̀mú

33 “Èyí ni májẹ̀mú tí èmi yóò bá ilé Israẹli dá

34 Kò ní sí pé ọkùnrin kan ń kọ́ àwọn ará ilé rẹ̀

35 Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

36 “Àyàfi tí ìlànà yìí bá kúrò níwájú mi,”

37 Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

38 “Ọjọ́ náà ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí wọn yóò tún ìlú yìí kọ́ fún mi láti ilé ìṣọ́ Hananeli dé igun ẹnu ibodè.

39 Okùn ìwọ̀n yóò sì nà jáde láti ibi gígùn lọ sí òkè Garebu yóò sì lọ sí Goa.

40 Gbogbo àfonífojì níbi tí wọ́n ń da òkú àti eérú sí, àti gbogbo àfonífojì Kidironi ní ìhà ìlà-oòrùn títí dé igun ẹnu ibodè ẹṣin yóò jẹ́ mímọ́ sí Olúwa. A kì yóò fa ìlú náà tu tàbí kí a wó o palẹ̀.”

Ler em outra tradução

Comparar lado a lado