1 Ṣùgbọ́n Jobu sì dáhùn wí pé,
2 “Báwo ni ìwọ ń ṣe ìrànlọ́wọ́ ẹni tí kò ní ipá,
3 Báwo ni ìwọ ń ṣe ìgbìmọ̀ fun ẹni tí kò ní ọgbọ́n,
4 Ta ni ó ràn ọ́ lọ́wọ́ láti sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí,
5 “Àwọn aláìlágbára ti isà òkú wárìrì,
6 Ìhòhò ni ipò òkú níwájú Ọlọ́run,
7 Òun ní o nà ìhà àríwá ọ̀run ní ibi òfúrufú,
8 Ó di omi pọ̀ nínú ìkùùkuu àwọsánmọ̀ rẹ̀ tí ó nípọn;
9 Ó sì fa ojú ìtẹ́ rẹ̀ sẹ́yìn,
10 Ó fi ìdè yí omi òkun ká,
11 Ọ̀wọ́n òpó ọ̀run wárìrì,
12 Ó fi ipá rẹ̀ dààmú omi Òkun;
13 Nípa ẹ̀mí rẹ̀ ni ó ti ṣe ọ̀run ní ọ̀ṣọ́;
14 Kíyèsi i, èyí ní òpin ọ̀nà rẹ̀;