1 Ìgbà náà ni Jobu sì dáhùn wí pé,
2 “Àní lónìí ni ọ̀ràn mi korò;
3 Háà! èmi ìbá mọ ibi tí èmí ìbá wá
4 Èmi ìbá sì to ọ̀ràn náà níwájú rẹ̀,
5 Èmi ìbá sì mọ ọ̀rọ̀ tí òun ìbá fi dá mi lóhùn;
6 Yóò ha fi agbára ńlá bá mi wíjọ́ bí?
7 Níbẹ̀ ni olódodo le è bá a wíjọ́,
8 “Sì wò ó, bí èmi bá lọ sí iwájú,
9 Ni apá òsì bí ó bá ṣiṣẹ́ níbẹ̀, èmi kò rí i,
10 Ṣùgbọ́n òun mọ ọ̀nà tí èmi ń tọ̀,
11 Ẹsẹ̀ mí ti tẹ̀lé ipasẹ̀ ìrìn rẹ̀;
12 Bẹ́ẹ̀ ni èmi kò padà sẹ́yìn kúrò nínú òfin ẹnu rẹ̀,
13 “Ṣùgbọ́n onínú kan ni òun, ta ni yóò sì yí i padà?
14 Nítòótọ́ ohun tí a ti yàn fún mi ní í ṣe;
15 Nítorí náà ni ara kò ṣe rọ̀ mí níwájú rẹ̀;
16 Nítorí pé Ọlọ́run ti pá mi ní àyà,
17 Nítorí tí a kò tí ì ké mi kúrò níwájú òkùnkùn,