1 Olúwa, èmi ké pè ọ́; yára wá sí ọ̀dọ̀ mi.
2 Jẹ́ kí àdúrà mi ó wá sí iwájú rẹ bí ẹbọ tùràrí
3 Fi ẹ̀ṣọ́ ṣọ́ ẹnu mi, Olúwa:
4 Má ṣe jẹ́ kí ọkàn mi fà sí ohun tí ń ṣe ibi,
5 Jẹ́ kí olódodo lù mí, ìṣeun ni ó jẹ́:
6 A ó ju àwọn alákòóso sílẹ̀ láti bẹ̀bẹ̀ òkúta,
7 Wọn yóò wí pé, “Bí ẹni tí ó la aporo sórí ilẹ̀,
8 Ṣùgbọ́n ojú mi ń bẹ lára rẹ, Olúwa Olódùmarè;
9 Pa mí mọ́ kúrò nínú okùn tí wọn ti dẹ sílẹ̀ fún mi,
10 Jẹ́ kí àwọn ẹni búburú ṣubú sínú àwọ̀n ara wọn,